Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 10:17-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ó sì tún ṣe ọ̀ọ́dúrún (300) aṣà wúrà lílù, pẹ̀lú òṣùwọ̀n wúrà mẹ́ta tí ó tàn sí aṣà kọ̀ọ̀kan. Ọba sì kó wọn sí ilé igbó Lébánónì.

18. Nígbà náà ni ọba sì ṣe ìtẹ́ èyín erin ńlá kan, ó sì fi wúrà dídára bò ó.

19. Ìtẹ́ náà sì ní àtẹ̀gùn mẹ́fà, èyín rẹ̀ sì ṣe róbótó lókè. Ní ibi ìjókòó méjèèjì náà ni irọpá wà, pẹ̀lú kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ ìkọ̀ọ̀kan wọn.

20. Kìnnìún méjìlá sì dúró níbi àtẹ̀gùn mẹ́fẹ̀ẹ̀fà ọ̀kọ̀kan ní òpin àtẹ̀gùn kọ̀ọ̀kan, kò tí ì sí irú rẹ̀ ní ìjọba kan rí.

21. Gbogbo ohun èlò mímu Sólómónì ọba sì jẹ́ wúrà àti gbogbo ohun èlò ààfin igbó Lébánónì sì jẹ́ kìkì wúrà. Kò sí ìkankan tí a fi fàdákà ṣe, nítorí a kò ka fàdákà sí nǹkankan ní gbogbo ọjọ́ Sólómónì.

22. Ọba sì ní ọkọ̀ Tásísì kan pẹ̀lú ọkọ̀ Hírámù ní òkun. Ẹ̀ẹ̀kan ní ọdún mẹ́ta ni ọkọ̀ Tásísì ń dé, tí ó ń mú wúrà àti fàdákà, eyín-erin àti ìnàkí àti ẹyẹ-ológe wá.

23. Sólómónì ọba sì pọ̀ ní ọrọ̀ àti ní ọgbọ́n ju gbogbo àwọn ọba ayé lọ.

24. Gbogbo ayé sì ń wá ojú Sólómónì láti gbọ́ ọgbọ́n tí Ọlọ́run ti fi sí i ní ọkàn.

25. Bí ọdún ṣe ń gorí ọdún olúkúlùkù àwọn tí ń wá sì ń mú ẹ̀bùn tirẹ̀ wá, ohun èlò fàdákà àti ohun èlò wúrà àti ẹ̀wù, àti tùràrí olóòórùn dídùn, ẹṣin àti ìbááka.

26. Sólómónì sì kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ; ó sì ní egbèje (1400) kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàata (13,000) ẹlẹ́ṣin, tí ó fi pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú rẹ̀ ní Jérúsálẹ́mù.

27. Ọba sì jẹ́ kí fàdákà pọ̀ ní Jérúsálẹ́mù bí òkúta, àti igi kédárì ni ó ṣe kí ó dàbí igi síkámórè tí ń bẹ ní àfonífojì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀.

28. A sì mú ẹṣin wá fún Sólómónì láti Éjíbítì ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, oníṣòwò ọba ni ó ń mú wọn wá fún òwe.

29. Wọ́n ń mú kẹ̀kẹ́ kan gòkè láti Éjíbítì wá fún ẹgbẹ̀ta (600) ṣékélì fàdákà àti ẹsin kan fún àádọ́jọ (150). Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún mú wọn wá fún ọba àwọn ọmọ Hítì àti ọba àwọn ọmọ Árámánì.

Ka pipe ipin 1 Ọba 10