Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 1:28-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Nígbà náà ni Dáfídì ọba wí pé, “Pe Bátíṣébà wọlé wá.” Ó sì wá ṣíwájú ọba, ó sì dúró níwájú rẹ̀.

29. Ọba sì búrá pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti wà ẹni tí ó ti gbàmí kúrò nínú gbogbo wàhálà,

30. Lónìí dandan ni èmi yóò gbé ohun tí mo ti fi Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì búra fún yọ pé: Sólómónì ọmọ rẹ ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, àti pé yóò jókòó lórí ìtẹ́ mi ní ipò mi.”

31. Nígbà náà ni Bátíṣébà tẹriba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba pé, “Kí Olúwa mi Dáfídì ọba kí ó pẹ́!”

32. Dáfídì ọba sì wí pé, “Ẹ pe Sadókù àlùfáà wọlé fún mi àti Nátanì wòlíì àti Bẹ́náyà ọmọ Jéhóíádà.” Nígbà tí wọ́n wá ṣíwájú ọba,

33. Ó sì wí fún wọn pé: “Ẹ mú àwọn ìránṣẹ́ Olúwa yín pẹ̀lú yín kí ẹ sì mú kí Sólómónì ọmọ mi kí ó gun ìbaka mi, kí ẹ sì mú-un sọ̀kalẹ̀ wá sí Gíhónì.

34. Níbẹ̀ ni Sádókù àlùfáà àti Nátanì wòlíì fi òróró yàn án ní ọba lórí Ísírẹ́lì. Ẹ fọn fèrè, kí ẹ sì ké pé, ‘Kí Sólómónì ọba kí ó pẹ́!’

Ka pipe ipin 1 Ọba 1