Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 19:7-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Wọ́n gba iṣẹ́ ẹgbẹ̀rin méjìlélọ́gbọ̀n kẹ̀kẹ́ àti agun-kẹ̀kẹ́ àti ọba Mákà pẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́-ọmọ ogun Rẹ̀ tí ó wá pàgọ́ ní ẹ̀bá Médébà, nígbà tí àwọn ará Ámónì kó jọ pọ̀ láti ìlú wọn, tí wọ́n sì jáde lọ fún ogun.

8. Ní gbígbọ́ eléyìí, Dáfídì rán Jóábù jáde pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ogun ọkùnrin tí ó le jà.

9. Àwọn ará Ámónì jáde wá, wọ́n sì dá isẹ́ ogun ní àbáwọlé sí ìlú ńlá wọn, nígbà tí àwọn ọba tí ó wá, fún rara wọn wà ni orílẹ̀ èdè tí ó sí sílẹ̀.

10. Jóábù ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun; Bẹ́ẹ̀ ni ọmọ ogun tí ó dára ní Ísírẹ́lì, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Ṣíríà.

11. Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Ábíṣáì arákùrin Rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ámónì.

12. Jóábù wí pé Tí àwọn ará Ṣíríà bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; Ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ámónì bá le jù fún ọ, Nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.

13. Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú Rẹ̀.

14. Nígbà náà Jóábù àti àwọn ọmọ ogun pẹ̀lú Rẹ̀ lọṣíwájú láti lọ jà pẹ̀lú àwọn ará Ṣíríà. Wọ́n sì sálọ kúrò níwájú Rẹ̀.

15. Nígbà ti àwọn ará Ámónì ri pé àwọn ará Ṣíríà ń sálọ, àwọn náà sálọ kúrò níwájú arákùnrin Rẹ̀ Ábíṣáì. Wọ́n sì wọ inú ìlú ńlá lọ. Bẹ́ẹ̀ ni Jóábù padà lọ sí Jérúsálẹ́mù.

16. Lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ará Ṣíríà rí wí pé àwọn Ísírẹ́lì ti lé wọn, wọ́n rán ìránṣẹ́. A sì mú àwọn ará Ṣíríà rékọjá odò wá, pẹ̀lú Ṣófákì alákóso ọmọ ogun Hádádésérì, tí ó ń darí wọn.

17. Nígbà tí a sọ fún Dáfídì nípa èyí, ó pe gbogbo Ísírẹ́lì jọ wọ́n sì rékọjá Jódánì; Ó lọ ṣíwájú wọn, ó sì fa ìlà ogun dojúkọ wọ́n. Dáfídì fa ìlà Rẹ̀ láti bá àwọn ará Ṣíríà jagun wọ́n sì doju ìjà kọ ọ́.

18. Ṣùgbọ́n wọ́n sálọ kúrò níwájú Ísírẹ́lì, Dáfídì sì pa ẹgbẹ̀rún méje agun-kẹ̀kẹ́ wọn àti ẹgbàá mẹ́rin ọmọ-ogun ẹlẹ́sẹ̀. Ó pa Ṣófákì alákóṣo ọmọ ogun wọn pẹ̀lú.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 19