5. Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀,ọkàn rẹ gbé sókèNitorí ọrọ̀ rẹ.
6. “ ‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Ọlọ́run wí:“ ‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n,pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run
7. Èmi yóò mú kí àwọn àjòjì dìde sí ọ,ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀ èdè;wọn yóò yọ idà wọn sí ọẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹwọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
8. Wọn yóò mú ọ sọ̀ kalẹ̀ wá sínú ihòìwọ yóò sì kú ikú gbígbónáàwọn tí a pa ní àárin òkun.
9. Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,”ní ojú àwọn tí ó pa ọ́?Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run,ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́
10. Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlàní ọwọ́ àwọn àjòjìÈmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Ọlọ́run wí.’ ”
11. Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
12. “Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tírè kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí:“ ‘Ìwọ jẹ́ àpẹrẹ ìjẹ́pípé náào kún fún ọgbọ́n,o sì pé ní ẹwà
13. Ìwọ ti wà ní Édẹ́nì, ọgbà Ọlọ́run;onírúurú òkúta iyebíye ni ìbora rẹ;sárídù, tópásì àti díámọ́ndì, bérílì oníkì,àti jásípérì, sáfírè, émérálídìàti káríbúnkílì, àti wúràìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dàláti ara wúrà,ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
14. A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù,torí èyí ni mo fi yàn ọ́.Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run;ìwọ rìn ni àárin òkúta amúbína,
15. Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹláti ọjọ́ tí a ti dá ọtítí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
16. Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹìwọ kún fún ìwà ipá;ìwọ sì dẹ́sẹ̀Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nùbí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run.Èmi sì pa ọ run,ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárin òkúta amúbínà
17. Ọkàn rẹ gbéraganítorí ẹwà rẹ.Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́nítorí dídára rẹ.Nítorí náà mo le ọ sórí ayé;mo sọ ọ di awò ojú níwájú àwọn ọba.