Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2. Kro 20:32-37 Yorùbá Bibeli (YCE)

32. O si rìn li ọ̀na Asa, baba rẹ̀, kò si yà kuro ninu rẹ̀, o nṣe eyi ti o tọ́ li oju Oluwa.

33. Sibẹ kò mu ibi giga wọnni kuro: pẹlupẹlu awọn enia na kò si fi ọkàn wọn fun Ọlọrun awọn baba wọn rara.

34. Ati iyokù iṣe Jehoṣafati, ti iṣaju ati ti ikẹhin, kiyẹsi i, a kọ wọn sinu iwe Jehu, ọmọ Hanani, a si ti fi i sinu iwe awọn ọba Israeli.

35. Ati lẹhin eyi ni Jehoṣafati, ọba Juda, dà ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ Ahasiah, ọba Israeli, ẹniti o ṣe buburu gidigidi:

36. O si dà ara rẹ̀ pọ̀ mọ ọ lati kan ọkọ̀ lati lọ si Tarṣiṣi: nwọn si kàn ọkọ̀ ni Esion-Geberi.

37. Nigbana ni Elieseri ọmọ Dodafah ti Mareṣa sọtẹlẹ si Jehoṣafati wipe, Nitori ti iwọ ti dá ara rẹ pọ̀ mọ Ahasiah, Oluwa ti ba iṣẹ rẹ jẹ. Awọn ọkọ̀ na si fọ́, nwọn kò si le lọ si Tarṣiṣi.

Ka pipe ipin 2. Kro 20