Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Esek 40:6-17 Yorùbá Bibeli (YCE)

6. Nigbana li o wá si ẹnu-ọ̀na ti o kọju si ọ̀na ila-õrun, o si gùn oke atẹ̀gun na lọ, o si wọ̀n iloro ẹnu ọ̀na, ti o jẹ ije kan ni ibú; ati iloro miran ti ẹnu-ọ̀na na, ti o jẹ ije kan ni ibú.

7. Yará kékèké si jẹ ije kan ni gigùn, ati ije kan ni ibú; ati lãrin yará kékèké igbọnwọ marun; àtẹwọ ẹnu-ọ̀na lẹba iloro ẹnu-ọ̀na ti inu si jẹ ije kan.

8. O si wọ̀n iloro ẹnu-ọ̀na ti inu, ije kan.

9. O si wọ̀n iloro ẹnu-ọ̀na, igbọnwọ mẹjọ; ati atẹrigba rẹ̀, igbọnwọ meji-meji; iloro ti ẹnu-ọ̀na na si mbẹ ninu.

10. Ati yará kékèké ẹnu-ọ̀na ti ọ̀na ila-õrun jẹ mẹta nihà ìhin, ati mẹta nihà ọhún; awọn mẹtẹta jẹ ìwọn kanna: awọn atẹrigba na jẹ ìwọn kanna niha ìhin ati niha ọhún.

11. O si wọ̀n ibu abawọle ẹnu-ọ̀na na, igbọnwọ mẹwa; ati gigùn ẹnu-ọ̀na na, igbọnwọ mẹtala.

12. Àye ti si mbẹ niwaju awọn yará kékèké na jẹ igbọnwọ kan nihà ìhin, àye na si jẹ igbọnwọ kan nihá ọhún; awọn yará kékèké na si jẹ igbọnwọ mẹfa nihà ìhin, ati igbọnwọ mẹfa niha ọhún.

13. O si wọ̀n ẹnu-ọ̀na na lati orule yará kékèké kan lọ de orule miran: ibú rẹ jẹ igbọnwọ mẹ̃dọgbọn, ilẹkùn dojukọ ilẹkùn.

14. O si ṣe atẹrigba ọlọgọta igbọnwọ, ani titi de atẹrigba àgbalá yi ẹnu-ọ̀na na ka.

15. Lati iwaju ẹnu-ọ̀na àtẹwọ titi fi de iwaju iloro ẹnu-ọ̀na ti inu, adọta igbọnwọ.

16. Awọn ferese tõro si mbẹ lara yará kékèké na, ati lara atẹrigba wọn ninu ẹnu-ọ̀na niha gbogbo ati pẹlu yará iloro: ferese pupọ si mbẹ niha inu gbogbo: igi ọpẹ si mbẹ lara olukuluku atẹrigbà.

17. O si mu mi wá si agbala ode, si kiyesi i, ọ̀pọlọpọ yará mbẹ nibẹ, a si fi okuta tẹ́ agbala na niha gbogbo: ọgbọ̀n yará ni mbẹ lori okuta itẹlẹ na.

Ka pipe ipin Esek 40