Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Esek 33:16-29 Yorùbá Bibeli (YCE)

16. A kì yio ṣe iranti gbogbo ẹ̀ṣẹ rẹ̀ ti o ti ndá fun u: on ti ṣe eyi ti o tọ ti o si yẹ; on o yè nitõtọ.

17. Sibẹ awọn ọmọ enia rẹ wipe, Ọ̀na Oluwa kò dọgba: ṣugbọn bi o ṣe ti wọn ni, ọ̀na wọn kò dọgba.

18. Nigbati olododo ba yipada kuro ninu ododo rẹ̀ ti o si ṣe aiṣedẽde, on o ti ipa rẹ̀ kú.

19. Ṣugbọn bi enia buburu bá yipada kuro ninu buburu rẹ̀, ti o si ṣe eyiti o tọ ti o si yẹ̀, on o ti ipa rẹ̀ wà lãye.

20. Sibẹ ẹnyin wi pe, Ọ̀na Oluwa kò dọgba, Ẹnyin ile Israeli, emi o dá olukuluku nyin li ẹjọ gẹgẹ bi ọ̀na rẹ̀.

21. O si ṣe li ọdun ikejila ikolọ wa, li oṣu kẹwa, li ọjọ karun oṣu, ẹnikan ti o ti salà jade ni Jerusalemu tọ̀ mi wá, o wipe, A kọlù ilu na.

22. Ọwọ́ Oluwa si wà lara mi li àṣalẹ, ki ẹniti o salà na to de; o si ti ṣi ẹnu mi, titi on fi wá sọdọ mi li owurọ; ẹnu mi si ṣi, emi kò si yadi mọ.

23. Nigbana ni ọ̀rọ Oluwa tọ̀ mi wá, wipe,

24. Ọmọ enia, awọn ti ngbe ahoro ile Israeli wọnni sọ, wipe, Abrahamu jẹ ẹnikan, on si jogun ilẹ na: ṣugbọn awa pọ̀, a fi ilẹ na fun wa ni ini.

25. Nitorina wi fun wọn pe, Bayi li Oluwa Ọlọrun wi, pe, ẹnyin njẹ ẹ̀jẹ mọ ẹran, ẹ si gbe oju nyin soke si awọn oriṣa nyin, ẹ si ta ẹjẹ silẹ, ẹnyin o ha ni ilẹ na?

26. Ẹnyin gbẹkẹle idà nyin, ẹ ṣe irira, olukuluku nyin bà obinrin aladugbò rẹ̀ jẹ́: ẹnyin o ha ni ilẹ na?

27. Iwọ wi bayi fun wọn pe, Bayi li Oluwa Ọlọrun wi; Bi emi ti wà, nitõtọ, awọn ti o wà ninu ahoro na yio ti ipa idà ṣubu, ẹniti o si wà ni gbangba oko li emi o si fi fun ẹranko lati pajẹ, awọn ti o si wà ninu odi ati ninu ihò okuta yio ti ipa ajakalẹ-àrun kú.

28. Nitoriti emi o sọ ilẹ na di ahoro patapata, ọ̀ṣọ nla agbara rẹ̀ kì yio si mọ, awọn oke Israeli yio si di ahoro, ti ẹnikan kì yio le là a kọja.

29. Nigbana ni nwọn o mọ̀ pe emi li Oluwa, nigbati mo ba ti sọ ilẹ na di ahoro patapata, nitori gbogbo irira ti nwọn ti ṣe.

Ka pipe ipin Esek 33