Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Esek 22:17-29 Yorùbá Bibeli (YCE)

17. Ọ̀rọ Oluwa si tọ̀ mi wá, wipe,

18. Ọmọ enia, ile Israeli di idarọ si mi: gbogbo wọn jẹ idẹ, ati tánganran, ati irin, ati ojé, lãrin ileru; ani nwọn jẹ idarọ fadaka.

19. Nitorina bayi li Oluwa Ọlọrun wi; Nitori ti gbogbo nyin di idarọ, kiyesi i, nitorina emi o ko nyin jọ si ãrin Jerusalemu.

20. Gẹgẹ bi nwọn ti ima ko fadaka, ati idẹ, ati irin, ati ojé, ati tánganran jọ si ãrin ileru, lati fin iná si i, ki a lè yọ́ ọ, bẹ̃ni emi o kó nyin ni ibinu mi, ati irúnu mi, emi o si fi nyin sibẹ emi o yọ́ nyin.

21. Nitotọ, emi o ko nyin jọ, emi o si fin iná ibinu mi si nyin lara, ẹ o si di yiyọ́ lãrin rẹ̀.

22. Bi a ti iyọ́ fadaka lãrin ileru, bẹ̃li a o yọ́ nyin lãrin rẹ̀; ẹnyin o si mọ̀ pe emi Oluwa li o ti dà irúnu mi si nyin lori.

23. Ọ̀rọ Oluwa si tọ̀ mi wá, wipe,

24. Ọmọ enia, sọ fun u, Iwọ ni ilẹ ti a kò gbá mọ́, ti a kò si rọ̀jo si i lori lọjọ ibinu.

25. Ìditẹ awọn wolĩ rẹ̀ wà lãrin rẹ̀, bi kiniun ti nke ramuramu ti nṣọdẹ; nwọn ti jẹ ọkàn run, nwọn ti kó ohun iṣura ati ohun iyebiye; nwọn ti sọ ọ̀pọlọpọ di opó fun u lãrin rẹ̀.

26. Awọn alufa rẹ̀ ti rú ofin mi, nwọn si fi sọ ohun mimọ́ mi di àilọwọ: nwọn kò fi ìyatọ sãrin ohun mimọ́ ati àilọwọ, bẹ̃ni nwọn kò fi ìyatọ hàn lãrin ohun aimọ́, ati mimọ́, nwọn si ti fi oju wọn pamọ kuro li ọjọ isimi mi, mo si di ẹmi àilọwọ lãrin wọn.

27. Awọn ọmọ-alade ãrin rẹ̀ dabi kõkò ti nṣọdẹ, lati tàjẹ silẹ, lati pa ọkàn run, lati jère aiṣõtọ.

28. Ati awọn wolĩ rẹ̀ ti fi ẹfun kùn wọn, nwọn nri asan, nwọn si nfọ afọ̀ṣẹ eke si wọn, wipe, Bayi li Oluwa Ọlọrun wi, nigbati o ṣepe Oluwa kò sọ̀rọ.

29. Awọn enia ilẹ na, ti lo ìwa-ininilara, nwọn si ja olè, nwọn si ti bi awọn talaka ati alaini ninu: nitõtọ, nwọn ti ni alejò lara lainidi.

Ka pipe ipin Esek 22