Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Luku 3:1-9 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ní ọdún kẹẹdogun tí Ọba Tiberiu ti wà lórí oyè, nígbà tí Pọntiu Pilatu jẹ́ gomina Judia, tí Hẹrọdu jẹ́ baálẹ̀ Galili, tí Filipi arakunrin rẹ̀ jẹ́ baálẹ̀ Ituria ati ti agbègbè Tirakoniti, Lusaniu jẹ́ baálẹ̀ Abilene;

2. Anasi ati Kayafa sì jẹ́ olórí alufaa. Johanu ọmọ Sakaraya gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọrun ní aṣálẹ̀ tí ó wà.

3. Ó bá ń kiri gbogbo ìgbèríko odò Jọdani, ó ń waasu pé kí àwọn eniyan ronupiwada, kí wọ́n ṣe ìrìbọmi, kí Ọlọrun lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì wọ́n.

4. Èyí rí bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti wà ninu ìwé ọ̀rọ̀ wolii Aisaya pé,“Ohùn ẹni tí ń kígbe ní aṣálẹ̀ pé,‘Ẹ la ọ̀nà fún Oluwa,ẹ ṣe ojú ọ̀nà tí ó tọ́ fún un láti rìn!

5. Gbogbo ọ̀gbun ni yóo jẹ́ dídígbogbo òkè gíga ati òkè kéékèèkéni yóo jẹ́ rírẹ̀ sílẹ̀.A óo tọ́ ibi tí ó bá ṣe kọ́rọ-kọ̀rọ,a óo sì sọ ọ̀nà tí kò bá dán tẹ́lẹ̀ di dídán

6. Gbogbo eniyan ni yóo rí ìgbàlà Ọlọrun.’ ”

7. Johanu ń sọ fún àwọn eniyan tí ó jáde lọ ṣe ìrìbọmi lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ìran paramọ́lẹ̀, ta ni ó kìlọ̀ fun yín láti sá fún ibinu tí ń bọ̀?

8. Ẹ fihàn ninu ìwà yín pé ẹ ti ronupiwada. Ẹ má bẹ̀rẹ̀ láti máa rò ninu ara yín pé, ‘A ní Abrahamu ní baba.’ Nítorí mò ń sọ fun yín pé Ọlọrun lè gbé ọmọ dìde fún Abrahamu láti inú òkúta wọnyi.

9. A sì ti fi àáké lé gbòǹgbò igi báyìí. Nítorí náà, igikígi tí kò bá máa so èso rere ni a óo gé lulẹ̀, tí a óo sì fi dáná.”

Ka pipe ipin Luku 3