Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Samuẹli Keji 23:1-7 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi nìyí; àní, ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ Dafidi, ọmọ Jese, tí a gbé ga ní Israẹli, ẹni àmì òróró Ọlọrun Jakọbu, olórin dídùn ní Israẹli:

2. “Ẹ̀mí OLUWA ń gba ẹnu mi sọ̀rọ̀,ọ̀rọ̀ rẹ̀ wà ní ẹnu mi.

3. Ọlọrun Israẹli ti sọ̀rọ̀,Àpáta Israẹli ti wí fún mi pé,‘Ẹni yòówù tí ó bá fi òtítọ́ jọba,tí ó ṣe àkóso pẹlu ìbẹ̀rù Ọlọrun,

4. a máa tàn sí wọn bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,bí oòrùn tí ó ń ràn ní òwúrọ̀ kutukutu,ní ọjọ́ tí kò sí ìkùukùu;ó dàbí òjò tí ń mú kí koríko hù jáde láti inú ilẹ̀.’

5. “Bẹ́ẹ̀ ni yóo rí fún arọmọdọmọ mi níwájú Ọlọrun,nítorí pé, ó ti bá mi dá majẹmu ayérayé nípa ohun gbogbo,majẹmu tí kò lè yipada, ati ìlérí tí kò ní yẹ̀.Yóo ṣe ohun tí mo fẹ́ fún mi.Yóo ràn mí lọ́wọ́, yóo fún mi ní ìfẹ́ ọkàn mi.

6. Ṣugbọn àwọn tí wọn kò mọ Ọlọrundàbí igi ẹ̀gún tí a gbé sọnù,kò sí ẹni tí ó lè fi ọwọ́ lásán gbá wọn mú.

7. Ẹni tí yóo fọwọ́ kan ẹ̀gún gbọdọ̀ lo ohun èlò tí a fi irin ṣe tabi igi ọ̀kọ̀,láti fi wọ́n jóná patapata.”

Ka pipe ipin Samuẹli Keji 23