Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemaya 3:16-29 BIBELI MIMỌ (BM)

16. Lẹ́yìn rẹ̀, Nehemaya ọmọ Asibuki, aláṣẹ ìdajì agbègbè Betisuri ṣe àtúnṣe dé itẹ́ Dafidi, títí dé ibi adágún àtọwọ́dá ati títí dé ilé àwọn akọni.

17. Lẹ́yìn rẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi wọnyi ṣe àtúnṣe ọ̀dọ̀ tiwọn ní ìsọ̀rí-ìsọ̀rí: Rehumu ọmọ Bani ṣe àtúnṣe apá ọ̀dọ̀ tirẹ̀, lẹ́yìn rẹ̀ ni Haṣabaya, aláṣẹ ìdajì agbègbè Keila ṣe àtúnṣe agbègbè tirẹ̀.

18. Àwọn arakunrin rẹ̀ ṣe àtúnṣe agbègbè tiwọn náà: Bafai ọmọ Henadadi, aláṣẹ ìdajì agbègbè Keila ṣe ti agbègbè rẹ̀.

19. Lẹ́yìn rẹ̀ ni Eseri ọmọ Jeṣua, aláṣẹ Misipa, náà ṣe àtúnṣe apá kan lára ibi ihamọra ní ibi igun odi.

20. Lẹ́yìn rẹ̀ ni Baruku, ọmọ Sabai, ṣe àtúnṣe láti apá ibi Igun odi títí dé ẹnu ọ̀nà ilé Eliaṣibu olórí alufaa.

21. Lẹ́yìn rẹ̀, Meremoti, ọmọ Uraya, ọmọ Hakosi, ṣe àtúnṣe apá tiwọn láti ẹnu ọ̀nà ilé Eliaṣibu títí dé òpin ilé Eliaṣibu.

22. Lẹ́yìn rẹ̀, àwọn alufaa, àwọn ará pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jọdani ṣe àtúnṣe ọ̀dọ̀ tiwọn.

23. Lẹ́yìn wọn ni Bẹnjamini ati Haṣubu ṣe àtúnṣe apá ibi tí ó kọjú sí ilé wọn. Lẹ́yìn wọn, Asaraya ọmọ Maaseaya, ọmọ Ananaya ṣe àtúnṣe ní ẹ̀gbẹ́ ilé tirẹ̀.

24. Lẹ́yìn rẹ̀, Binui, ọmọ Henadadi ṣe àtúnṣe apá ọ̀dọ̀ tirẹ̀: láti ilé Asaraya títí dé ibi Igun Odi.

25. Palali, ọmọ Usai ṣe àtúnṣe ibi tí ó kọjú sí Igun Odi ati ilé ìṣọ́, láti òkè ilé ọba níbi ọgbà àwọn olùṣọ́. Lẹ́yìn rẹ̀ ni Pedaaya, ọmọ Paroṣi,

26. ati àwọn iranṣẹ tẹmpili tí wọn ń gbé Ofeli ṣe àtúnṣe tiwọn dé ibi tí ó kọjú sí Ẹnubodè Omi, ní ìhà ìlà oòrùn ati ilé ìṣọ́ tí ó yọgun jáde títí dé ibi odi Ofeli.

27. Lẹ́yìn náà ni àwọn ará Tekoa ṣe àtúnṣe apá ibi tí ó kọjú sí ilé ìṣọ́ tí ó yọgun jáde títí dé Ofeli.

28. Àwọn alufaa ni wọ́n tún Òkè Ẹnubodè Ẹṣin ṣe, olukuluku tún ibi tí ó kọjú sí ilé rẹ̀ ṣe.

29. Lẹ́yìn wọn, Sadoku, ọmọ Imeri, ṣe àtúnṣe ibi tí ó kọjú sí ilé tirẹ̀.Lẹ́yìn rẹ̀ ni Ṣemaaya, ọmọ Ṣekanaya, olùṣọ́ ẹnu ọ̀nà ìhà ìlà oòrùn, ṣe àtúnṣe ọ̀dọ̀ tirẹ̀.

Ka pipe ipin Nehemaya 3