Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 34:15-35 BIBELI MIMỌ (BM)

15. gbogbo eniyan ni yóo ṣègbé,tí wọn yóo sì pada di erùpẹ̀.

16. “Bí ẹ bá ní òye, ẹ gbọ́ ohun tí mo fẹ́ sọ.

17. Ǹjẹ́ ẹni tí ó kórìíra ìdájọ́ ẹ̀tọ́ lè jẹ́ olórí?Àbí ẹ lè dá olódodo ati alágbára lẹ́bi?

18. Ẹni tí ó tó pe ọba ní eniyan lásán,tí ó tó pe ìjòyè ní ẹni ibi;

19. ẹni tí kì í ṣe ojuṣaaju fún àwọn ìjòyè,tí kì í sì í ka ọlọ́rọ̀ sí ju talaka lọ,nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn.

20. Wọn á kú ikú òjijì, ní ọ̀gànjọ́ òru;á mi gbogbo eniyan jìgìjìgì, wọn a sì kú.Ikú á mú àwọn alágbára lọ láì jẹ́ pé eniyan fi ọwọ́ kàn wọ́n.

21. Nítorí pé ojú rẹ̀ tó gbogbo ọ̀nà tí eniyan ń tọ̀,ó sì rí gbogbo ìrìn ẹsẹ̀ wọn.

22. Kò sí ibi òkùnkùn biribiri kankan,tí àwọn eniyan burúkú lè fi ara pamọ́ sí.

23. Nítorí Ọlọrun kò nílò láti yan àkókò kan fún ẹnikẹ́ni,láti wá siwaju rẹ̀ fún ìdájọ́.

24. Á pa àwọn alágbára run láìṣe ìwádìí wọn,á sì fi àwọn ẹlòmíràn dípò wọn.

25. Nítorí pé ó mọ iṣẹ́ ọwọ́ wọn,á bì wọ́n ṣubú lóru, wọn á sì parun.

26. Á máa jẹ wọ́n níyà ní gbangba,nítorí ìwà ibi wọn.

27. Nítorí pé wọ́n kọ̀ láti tẹ̀lé e,wọn kò náání ọ̀nà rẹ̀ kankan,

28. wọ́n ń jẹ́ kí àwọn talaka máa kígbe sí Ọlọrun,a sì máa gbọ́ igbe àwọn tí a ni lára.

29. “Bí Ọlọrun bá dákẹ́,ta ló lè bá a wí?Nígbà tí ó bá fi ojú pamọ́,orílẹ̀-èdè tabi eniyan wo ló lè rí i?

30. Kí ẹni ibi má baà lè ṣe àkóso,kí ó má baà kó àwọn eniyan sinu ìgbèkùn.

31. “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tíì sọ fún Ọlọrun pé,‘Mo ti jìyà rí, n kò sì ní gbẹ̀ṣẹ̀ mọ́.

32. Kọ́ mi ní ohun tí n kò rí,bí mo bá ti ṣẹ̀ rí, n kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́?’

33. Ṣé yóo san ẹ̀san fún ọ lọ́nà tí ó tẹ́ ọ lọ́rùn,nítorí pé o kọ̀ ọ́?Nítorí ìwọ ni o gbọdọ̀ yan ohun tí ó bá wù ọ́, kì í ṣe èmi,nítorí náà, sọ èrò ọkàn rẹ fún wa.

34. Àwọn tí wọ́n lóye yóo sọ fún mi,àwọn ọlọ́gbọ́n tí wọn ń gbọ́ mi yóo sọ pẹlu pé,

35. ‘Jobu ń sọ̀rọ̀ láìní ìmọ̀,ó ń sọ̀rọ̀ láìní òye tí ó jinlẹ̀.’

Ka pipe ipin Jobu 34