Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jobu 14:3-15 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Ṣé irú ẹni bẹ́ẹ̀ ni o dojú kọ,tí ò ń bá ṣe ẹjọ́?

4. Ta ló lè mú ohun mímọ́ jádeláti inú ohun tí kò mọ́?Kò sí ẹni náà.

5. Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá ọjọ́ fún un,tí o mọ iye oṣù rẹ̀,tí o sì ti pa ààlà tí kò lè rékọjá.

6. Mú ojú rẹ kúrò lára rẹ̀, kí ó lè sinmi,kí ó sì lè gbádùn ọjọ́ ayé rẹ̀ bí alágbàṣe.

7. “Nítorí pé ìrètí ń bẹ fún igi tí wọn gé,yóo tún pada rúwé,ẹ̀ka rẹ̀ kò sì ní ṣe aláìsọ.

8. Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ògbólógbòó ninu ilẹ̀,tí kùkùté rẹ̀ sì kú,

9. bí ó bá ti gbóòórùn omi, yóo sọ,yóo sì yọ ẹ̀ka bí ọ̀dọ́ irúgbìn.

10. Ṣugbọn bí eniyan bá kú, a óo tẹ́ ẹ sinu ibojì,bí ó bá ti gbẹ́mìí mì, ó di aláìsí.

11. Bí adágún omi tíí gbẹ,ati bí odò tíí ṣàn lọ, tí sìí gbẹ,

12. bẹ́ẹ̀ ni eniyan ṣe é sùn,tí kì í sìí jí mọ́,títí tí ọ̀run yóo fi kọjá lọ, kò ní jí,tabi kí ó tilẹ̀ rúnra láti ojú oorun.

13. Ìbá sàn kí o fi mí pamọ́ sinu ibojì,kí o pa mí mọ́ títí inú rẹ yóo fi rọ̀,ò bá dá àkókò fún mi, kí o sì ranti mi.

14. Bí eniyan bá kú, ǹjẹ́ yóo tún jí mọ́?N óo dúró ní gbogbo ọjọ́ làálàá mi,n óo máa retí, títí ọjọ́ ìdáǹdè mi yóo fi dé.

15. O óo pè mí, n ó sì dá ọ lóhùn,o óo máa ṣe àfẹ́rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

Ka pipe ipin Jobu 14