Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 9:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Orí mi ìbá jẹ́ kìkì omi,kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé;tọ̀sán-tòru ni ǹ bá fi máa sọkún,nítorí àwọn eniyan mi tí ogun ti pa.

2. Ìbá ṣe pé mo ní ilé èrò kan ninu aṣálẹ̀,ǹ bá kó àwọn eniyan mi dà sílẹ̀ níbẹ̀,ǹ bá sì kúrò lọ́dọ̀ wọn;nítorí alágbèrè ni gbogbo wọn,ati àgbájọ àwọn alárèékérekè eniyan.

3. Bí ẹni kẹ́ ọrun ni wọ́n kẹ́ ahọ́n wọn,láti máa fọ́n irọ́ jáde bí ẹni ta ọfà;dípò òtítọ́ irọ́ ní ń gbilẹ̀ ní ilẹ̀ náà.OLUWA ní,“Wọ́n ń tinú ibi bọ́ sinu ibi,wọn kò sì mọ̀ èmi OLUWA.”

4. Kí olukuluku ṣọ́ra lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,kí ó má sì gbẹ́kẹ̀lé arakunrin rẹ̀ kankan.Nítorí pé ajinnilẹ́sẹ̀ ni gbogbo arakunrin,a-fọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-ba-tẹni-jẹ́ sì ni gbogbo aládùúgbò.

Ka pipe ipin Jeremaya 9