Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 49:23-29 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Ohun tí OLUWA sọ nípa Damasku nìyí, Ó ní,“Ìdààmú dé bá Hamati ati Aripadi,nítorí pé wọ́n gbọ́ ìròyìn burúkú:Jìnnìjìnnì dà bò wọ́n, ọkàn wọn sì dàrú,bí omi òkun tí kò lè dákẹ́ jẹ́ẹ́.

24. Àárẹ̀ mú Damasku,ó pẹ̀yìndà pé kí ó máa sálọ,ṣugbọn ìpayà mú un,ìrora ati ìbànújẹ́ sì dé bá a, bí obinrin tí ń rọbí.

25. Ẹ wò ó bí ìlú olókìkí tí ó kún fún ayọ̀, ṣe di ibi ìkọ̀sílẹ̀!

26. Àwọn ọdọmọkunrin Damasku yóo ṣubú ní gbàgede rẹ̀ ní ọjọ́ náà,gbogbo àwọn ọmọ ogun ibẹ̀ yóo sì parun ni;Èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

27. N óo dáná sun odi Damasku,yóo sì jó ibi ààbò Benhadadi.”

28. OLUWA sọ nípa Kedari ati àwọn ìjọba Hasori tí Nebukadinesari ọba Babiloni ṣẹgun pé,“Ẹ dìde kí ẹ gbógun ti Kedari!Ẹ pa àwọn ará ìlà oòrùn run!

29. Ogun yóo kó àgọ́ wọn ati àwọn ẹran ọ̀sìn wọn lọ,ati àwọn aṣọ àgọ́, ati ohun ìní wọn;Ọ̀tá yóo kó ràkúnmí wọn lọ,àwọn eniyan yóo máa kígbe sí wọn pé,‘Ìpayà wà ní gbogbo àyíká.’

Ka pipe ipin Jeremaya 49