Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 49:10-22 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Ṣugbọn mo ti tú àwọn ọmọ Esau sí ìhòòhò,Mo ti sọ ibi tí wọn ń sápamọ́ sí di gbangba,wọn kò sì rí ibi sápamọ́ sí mọ́.Àwọn ọmọ wọn ti parun,pẹlu àwọn arakunrin wọn ati àwọn aládùúgbò wọn;àwọn pàápàá sì ti di àwátì.

11. Fi àwọn ọmọ rẹ, aláìníbaba sílẹ̀,n óo pa wọ́n mọ́ láàyè,sì jẹ́ kí àwọn opó rẹ gbẹ́kẹ̀lé mi.

12. “Bí àwọn tí kò yẹ kí wọ́n jìyà bá jìyà, ṣé ìwọ wá lè lọ láìjìyà? O kò ní lọ láìjìyà, dájúdájú ìyà óo jẹ ọ́.

13. Nítorí pé mo ti fi ara mi búra, èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀, pé Bosira yóo di àríbẹ̀rù ati ohun ẹ̀gàn, ahoro ati ohun àmúgégùn-ún; àwọn ìlú rẹ̀ yóo sì di ahoro títí lae.”

14. Mo ti gbọ́ ìròyìn láti ọ̀dọ̀ OLUWA,wọ́n ti rán ikọ̀ kan sí àwọn orílẹ̀-èdè,wọ́n ní kí wọn kéde pé,“OLUWA ní, ‘Ẹ kó ara yín jọ, kí ẹ kọlu Edomu,ẹ dìde, kí ẹ gbógun tì í!

15. Nítorí pé n óo sọ ọ́ di kékeréláàrin àwọn orílẹ̀-èdè,o óo sì di yẹpẹrẹ,láàrin àwọn ọmọ eniyan.

16. Ẹ̀rù tí ó wà lára rẹ, ati ìgbéraga ọkàn rẹ ti tàn ọ́ jẹ,ìwọ tí ò ń gbé pàlàpálá àpáta,tí o fi góńgó orí òkè ṣe ibùgbé.Bí o tilẹ̀ kọ́ ìtẹ́ rẹ sí ibi gíga, bíi ti ẹyẹ idì,n óo fà ọ́ lulẹ̀ láti ibẹ̀.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.’ ”

17. OLUWA ní, “Edomu yóo sì di ibi àríbẹ̀rù, ẹ̀rù yóo máa ba gbogbo àwọn tí wọ́n bá gba ibẹ̀ kọjá, wọn yóo máa pòṣé nítorí ibi tí ó dé bá a.

18. Yóo rí fún un bí ó ti rí fún Sodomu ati Gomora ati àwọn ìlú agbègbè wọn tí ó parun. Ẹnikẹ́ni kò ní gbé ibẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò ní dé sibẹ. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

19. Wò ó, bí kinniun tií yọ ní aginjù odò Jọdani láti kọlu agbo aguntan, bẹ́ẹ̀ ni n óo yọ sí Edomu n óo sì mú kí ó sá kúrò lórí ilẹ̀ rẹ̀ lójijì. N óo sì yan ẹnikẹ́ni tí ó bá wù mí láti máa ṣe àkóso ibẹ̀; nítorí ta ló dàbí mi? Ta ló lè yẹ̀ mí lọ́wọ́ wò? Olùṣọ́-aguntan wo ló lè dúró dè mí?

20. Nítorí náà, ẹ gbọ́ ète tí OLUWA pa lórí Edomu, ati èrò rẹ̀ lórí àwọn tí wọn ń gbé Temani. A óo kó agbo ẹran wọn lọ tọmọtọmọ, ibùjẹ àwọn ẹran wọn yóo parun nítorí tiwọn.

21. Ariwo wíwó odi Edomu wọn yóo mi ilẹ̀ tìtì, a óo sì gbọ́ ìró rẹ̀ títí dé etí òkun pupa.

22. Wò ó! Ẹnìkan yóo fò bí ẹyẹ idì, yóo na ìyẹ́ rẹ̀ sórí Bosira, ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ọmọ ogun Edomu yóo dàbí ọkàn obinrin tí ń rọbí.”

Ka pipe ipin Jeremaya 49