Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 49:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ohun tí OLUWA sọ nípa àwọn ará Amoni nìyí: Ó ní,“Ṣé Israẹli kò lọ́mọ ni?Tabi kò ní àrólé?Kí ló dé tí àwọn tí ń bọ Milikomu ṣe gba ilẹ̀ ẹ̀yà Gadi,tí wọ́n sì fi àwọn ìlú Gadi ṣe ibùjókòó?

2. Nítorí náà, wò ó, àkókò ń bọ̀ tí n óo jẹ́ kí ariwo ogun sọ, ní Raba ìlú àwọn ọmọ Amoni;Raba yóo di òkítì àlàpà,a óo sì dáná sun àwọn ìgbèríko rẹ̀;Israẹli yóo wá pada fi ogun kó àwọn tí wọ́n kó o lẹ́rú.

3. Sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn, ìwọ Heṣiboni,nítorí pé ìlú Ai ti parun!Ẹ sọkún, ẹ̀yin ọmọbinrin Raba!Ẹ ró aṣọ ọ̀fọ̀,ẹ máa sọkún, kí ẹ sì máa sá sókè sódò láàrin ọgbà!Nítorí pé oriṣa Moleki yóo lọ sí ìgbèkùn,pẹlu àwọn babalóòṣà rẹ̀ ati àwọn ìjòyè ní ibi ìsìn rẹ̀.

4. Kí ló dé tí ò ń fọ́nnu nípa agbára rẹ,ipá rẹ ti pin, ìwọ olóríkunkun ọmọbinrinìwọ tí o gbójú lé ọrọ̀ rẹ,tí ò ń wí pé, ‘Ta ló lè dojú kọ mí?’

Ka pipe ipin Jeremaya 49