Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 4:9-24 BIBELI MIMỌ (BM)

9. OLUWA ní, “Tó bá di ìgbà náà, ojora yóo mú ọba ati àwọn ìjòyè, àwọn alufaa yóo dààmú, ẹnu yóo ya àwọn wolii.”

10. Mo bá dáhùn pé, “Háà, OLUWA Ọlọrun, àṣé ò ń tan àwọn eniyan wọnyi, ati àwọn ará Jerusalẹmu ni, nígbà tí o sọ fún wọn pé, yóo dára fún wọn; àṣé idà ti dé ọrùn wọn!”

11. A óo wí fún àwọn eniyan yìí, ati àwọn ará Jerusalẹmu ní ìgbà náà pé afẹ́fẹ́ gbígbóná kan ń fẹ́ bọ̀ láti orí àwọn òkè, ninu pápá, ó ń fẹ́ bọ̀ sọ́dọ̀ àwọn eniyan mi; kì í ṣe afẹ́fẹ́ lásán tíí fẹ́ pàǹtí ati ìdọ̀tí dànù.

12. Ìjì tí yóo ti ọ̀dọ̀ mi wá yóo le jù bẹ́ẹ̀ lọ. Nisinsinyii èmi ni mò ń fi ọ̀rọ̀ mi dá wọn lẹ́jọ́.

13. Ẹ wò ó! Ó ń bọ̀ bí ìkùukùu,kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ dàbí ìjì.Àwọn ẹṣin rẹ̀ yára ju àṣá lọ.A gbé, nítorí ìparun dé bá wa.

14. Ìwọ Jerusalẹmu, fọ ibi dànù kúrò lọ́kàn rẹ,kí á lè gbà ọ́ là.Yóo ti pẹ́ tó tí èrò burúkú yóo fi máa wà lọ́kàn rẹ?

15. Nítorí a gbọ́ ohùn kan láti ilẹ̀ Dani,tí ń kéde ibi láti òkè Efuraimu.

16. Ẹ kìlọ̀ fún àwọn orílẹ̀-èdè pé ó ń bọ̀,kéde fún Jerusalẹmu pé,àwọn ológun tí ń dó ti ìlú ń bọ̀, láti ilẹ̀ òkèèrè.Wọ́n ń kọ lálá sí àwọn ìlú Juda.

17. Wọ́n yí i ká bí àwọn tí ó ń ṣọ́ oko,nítorí pé ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí OLUWA.OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

18. Ìrìn ẹsẹ̀ rẹ ati ìwà rẹni ó mú kí àwọn nǹkan wọnyi dé bá ọ.Ìjìyà rẹ nìyí, ó sì korò;ó ti dé oókan àyà rẹ.

19. Oró ò! Oró ò!Mò ń jẹ̀rora!Àyà mi ò!Àyà mi ń lù kìkìkì,n kò sì lè dákẹ́;nítorí mo gbọ́ ìró fèrè ogun, ati ariwo ogun.

20. Àjálù ń ṣubú lu àjálù,gbogbo ilẹ̀ ti parun.Lójijì àgọ́ mi wó lulẹ̀,aṣọ títa mi sì fàya ní ìṣẹ́jú kan.

21. Yóo ti pẹ́ tó tí n óo máa wo àsíá ogun,tí n óo sì máa gbọ́ fèrè ogun?

22. OLUWA ní, “Nítorí pé àwọn eniyan mi gọ̀,wọn kò mọ̀ mí.Òmùgọ̀ ọmọ ni wọ́n;wọn kò ní òye.Ọgbọ́n àtiṣe ibi kún inú wọn:ṣugbọn wọn kò mọ rere ṣe.”

23. Mo bojú wo ilé ayé, ilé ayé ṣófo,ó rí júujùu;mo ṣíjú wo ojú ọ̀run,kò sí ìmọ́lẹ̀ níbẹ̀.

24. Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n ń mì tìtì,gbogbo òkè kéékèèké ń sún lọ síhìn-ín sọ́hùn-ún.

Ka pipe ipin Jeremaya 4