Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 3:2-9 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Ẹ gbójú sókè kí ẹ wo gbogbo òkè yíká,ibo ni ẹ kò tíì ṣe àgbèrè dé?Ẹ̀ ń dúró de olólùfẹ́ lẹ́bàá ọ̀nà,bí àwọn obinrin Arabia ninu aṣálẹ̀.Ẹ ti fi ìṣekúṣe yín ba ilẹ̀ náà jẹ́.

3. Nítorí náà ni òjò kò ṣe rọ̀,tí òjò àkọ́rọ̀ kò rọ̀ ní àkókò tí ó yẹ.Sibẹsibẹ, ẹ̀ ń gbéjú gbéré bí aṣẹ́wó,ojú kò sì tì yín.

4. Israẹli, o wá ń pè mí nisinsinyii, ò ń sọ pé,‘Ìwọ ni baba mi, ìwọ ni ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.

5. Ṣé o kò ní dáwọ́ ibinu rẹ dúró ni?Tabi títí ayé ni o óo fi máa bínú?’Lóòótọ́ o ti sọ bẹ́ẹ̀ tẹ́lẹ̀,ṣugbọn o ti ṣe ìwọ̀n ibi tí o lè ṣe.”

6. OLUWA sọ fún mi ní ìgbà ayé ọba Josaya pé: “Ṣé o rí ohun tí Israẹli, alaiṣootọ ẹ̀dá ṣe? Ṣé o rí i bí ó tí ń lọ ṣe àgbèrè lórí gbogbo òkè ati lábẹ́ gbogbo igi tútù?

7. Mo rò pé yóo pada tọ̀ mí wá, lẹ́yìn tí ó bá ṣe àgbèrè rẹ̀ tán ni; ṣugbọn kò pada; Juda arabinrin rẹ̀, alaiṣootọ sì rí i,

8. ó mọ̀ pé nítorí ìwà àgbèrè Israẹli, alaiṣootọ, ni mo ṣe lé e jáde, tí mo sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Sibẹsibẹ Juda tí òun pàápàá jẹ́ alaiṣootọ, kò bẹ̀rù, òun náà lọ ṣe àgbèrè.

9. Nítorí pé ìwà àgbèrè jẹ́ nǹkan kékeré lójú rẹ̀, ó ṣe àgbèrè pẹlu òkúta ati igi ó sì ba ilẹ̀ náà jẹ́.

Ka pipe ipin Jeremaya 3