Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 2:20-26 BIBELI MIMỌ (BM)

20. OLUWA wí pé,“Nítorí pé ó ti pẹ́ tí ẹ ti bọ́ àjàgà yín,tí ẹ sì ti tú ìdè yín;tí ẹ sọ pé, ẹ kò ní sìn mí.Ẹ̀ ń lọ káàkiri lórí gbogbo òkè,ati lábẹ́ gbogbo igi tútù;ẹ̀ ń foríbalẹ̀, ẹ̀ ń ṣe bíi panṣaga.

21. Sibẹ mo gbìn yín gẹ́gẹ́ bí àjàrà tí mo fẹ́,tí èso rẹ̀ dára.Báwo ni ẹ ṣe wá yipada patapata,tí ẹ di àjàrà igbó tí kò wúlò?

22. Bí ẹ tilẹ̀ fi eérú fọ ara yín,tí ẹ sì fi ọpọlọpọ ọṣẹ wẹ̀,sibẹ, àbààwọ́n ẹ̀bi yín wà níwájú mi.

23. Báwo ní ẹ ṣe lè wí pé ẹ kì í ṣe aláìmọ́;ati pé ẹ kò tẹ̀lé àwọn oriṣa Baali?Ẹ wo irú ìwà tí ẹ hù ninu àfonífojì,kí ẹ ranti gbogbo ibi tí ẹ ṣebí ọmọ ràkúnmí tí ń lọ, tí ń bọ̀;tí ń tọ ipa ọ̀nà ara rẹ̀.

24. Ẹ dàbíi Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́, tí aṣálẹ̀ ti mọ́ lára,tí ń ṣí imú kiri,nígbà tí ó ń wa akọ tí yóo gùn ún.Ta ló lè dá a dúró?Kí akọ tí ó bá ń wá amá wulẹ̀ ṣe ara rẹ̀ ní wahala,nítorí yóo yọjú nígbà tí àkókò gígùn rẹ̀ bá tó.

25. Má rìn láìwọ bàtà, Israẹli,má sì jẹ́ kí òùngbẹ gbẹ ọ́.Ṣugbọn o sọ pé, ‘Kò sí ìrètí,nítorí àjèjì oriṣa ni mo fẹ́,n óo sì wá wọn kiri.’ ”

26. OLUWA ní, “Bí ojú tíí ti olè nígbà tí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́,bẹ́ẹ̀ ni ojú yóo tì yín, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.Àtẹ̀yin ati àwọn ọba yín, ati àwọn ìjòyè yín,ati àwọn alufaa yín, ati àwọn wolii yín;

Ka pipe ipin Jeremaya 2