Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremaya 15:2-5 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Bí wọ́n bá bi ọ́ pé níbo ni kí àwọn ó lọ, sọ fún wọn pé èmi OLUWA ní,‘Àwọn tí wọn yóo kú ikú àjàkálẹ̀ àrùn,kì àjàkálẹ̀ àrùn pa wọ́n;àwọn tí wọn yóo kú ikú ogun,kí ogun pa wọ́n.Àwọn tí wọn yóo kú ikú ìyàn,kí ìyàn pa wọ́n;àwọn tí wọn yóo lọ sí ìgbèkùn,kí ogun kó wọn lọ.’

3. Oríṣìí ìparun mẹrin ni n óo jẹ́ kí ó dé bá wọn: idà óo pa wọ́n, ajá óo fà wọ́n ya, àwọn ẹyẹ ati àwọn ẹranko óo jẹ wọ́n ní àjẹrun.

4. N óo sọ wọ́n di ohun tí ó bani lẹ́rù fún gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé, nítorí ohun tí Manase, ọmọ Hesekaya, ọba Juda, ṣe ní Jerusalẹmu.”

5. OLUWA ní,“Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu, ta ni yóo ṣàánú yín?Ta ni yóo dárò yín?Ta ni yóo ya ọ̀dọ̀ yín, láti bèèrè alaafia yín?

Ka pipe ipin Jeremaya 15