Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 28:8-26 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ẹni tí ó ń fi kún ọrọ̀ rẹ̀ nípa gbígba èléati èrè jíjẹ ní ọ̀nà èrú,ń kó ọrọ̀ náà jọ fún ẹni tí yóo ṣàánú àwọn talaka.

9. Ẹni tí ó kọ etí dídi sí òfin Ọlọrun,adura rẹ̀ pàápàá yóo di ìríra sí Ọlọ́run.

10. Ẹni tí ó ṣi olódodo lọ́nà lọ sinu ibi,yóo já sinu kòtò tí òun fúnrarẹ̀ gbẹ́ sílẹ̀,ṣugbọn aláìlẹ́bi eniyan yóo jogún ire.

11. Ọlọ́rọ̀ gbọ́n lójú ara rẹ̀,ṣugbọn talaka tí ó gbọ́n yóo rídìí rẹ̀.

12. Nígbà tí olódodo bá borí, àwọn eniyan á yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀,ṣugbọn nígbà tí ìkà bá dìde, àwọn eniyan á sá pamọ́.

13. Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣe rere,ṣugbọn ẹni tí ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,tí ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, yóo rí àánú gbà.

14. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó ń bẹ̀rù OLUWA nígbà gbogbo,ṣugbọn ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le yóo bọ́ sinu ìyọnu.

15. Ọba burúkú tí ó jọba lórí àwọn talaka,dàbí kinniun tí ń bú ramúramù,tabi ẹranko beari tí inú ń bí.

16. Ìkà, aninilára ni olórí tí kò ní òye,ṣugbọn ẹ̀mí ẹni tí ó bá kórìíra à ń jèrè lọ́nà èrú yóo gùn.

17. Bí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan bá ń da eniyan láàmú,yóo di ìsáǹsá ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀,kí ẹnikẹ́ni má ṣe ràn án lọ́wọ́.

18. Ẹni tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inú yóo rí ìgbàlà,ṣugbọn ẹni tí ń rìn ségesège yóo ṣubú sinu kòtò.

19. Ẹni tí ń ṣiṣẹ́ oko dáradára, yóo ní oúnjẹ pupọ,ṣugbọn ẹni tí ń fi àkókò rẹ̀ ṣòfò yóo di talaka.

20. Olóòótọ́ yóo ní ibukun lọpọlọpọ,ṣugbọn ẹni tí ń kánjú àtilówó, kò ní lọ láìjìyà.

21. Ojuṣaaju kò dára,sibẹ oúnjẹ lè mú kí eniyan ṣe ohun tí kò tọ́.

22. Ahun a máa sáré ati ní ọrọ̀,láìmọ̀ pé òṣì ń bọ̀ wá ta òun.

23. Ẹni tí ó bá eniyan wí,yóo rí ojurere níkẹyìn,ju ẹni tí ń pọ́n eniyan lọ.

24. Ẹni tí ó ja ìyá tabi baba rẹ̀ lólè,tí ó ní, “Kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀”,ẹlẹgbẹ́ apanirun ni.

25. Olójúkòkòrò eniyan a máa dá ìjà sílẹ̀,ṣugbọn ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé OLUWA yóo ṣe rere.

26. Òmùgọ̀ ni ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé ara rẹ̀,ẹni tí ń fi ọgbọ́n rìn yóo là.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 28