Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 28:4-17 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Àwọn tí wọ́n kọ òfin sílẹ̀ni wọ́n máa ń yin àwọn eniyan burúkú,ṣugbọn àwọn tí wọn ń pa òfin mọ́ máa ń dojú ìjà kọ wọ́n.

5. Òye ìdájọ́ òdodo kò yé àwọn eniyan burúkú,ṣugbọn ó yé àwọn tí ń wá OLUWA yékéyéké.

6. Talaka tí ń rìn pẹlu òtítọ́ inúsàn ju ọlọ́rọ̀ tí ń hùwà àgàbàgebè lọ.

7. Ọlọ́gbọ́n ọmọ ni ọmọ tí ó pa òfin mọ́,ṣugbọn ẹni tí ń bá àwọn wọ̀bìà rìn, ń dójúti baba rẹ̀.

8. Ẹni tí ó ń fi kún ọrọ̀ rẹ̀ nípa gbígba èléati èrè jíjẹ ní ọ̀nà èrú,ń kó ọrọ̀ náà jọ fún ẹni tí yóo ṣàánú àwọn talaka.

9. Ẹni tí ó kọ etí dídi sí òfin Ọlọrun,adura rẹ̀ pàápàá yóo di ìríra sí Ọlọ́run.

10. Ẹni tí ó ṣi olódodo lọ́nà lọ sinu ibi,yóo já sinu kòtò tí òun fúnrarẹ̀ gbẹ́ sílẹ̀,ṣugbọn aláìlẹ́bi eniyan yóo jogún ire.

11. Ọlọ́rọ̀ gbọ́n lójú ara rẹ̀,ṣugbọn talaka tí ó gbọ́n yóo rídìí rẹ̀.

12. Nígbà tí olódodo bá borí, àwọn eniyan á yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀,ṣugbọn nígbà tí ìkà bá dìde, àwọn eniyan á sá pamọ́.

13. Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣe rere,ṣugbọn ẹni tí ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,tí ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, yóo rí àánú gbà.

14. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó ń bẹ̀rù OLUWA nígbà gbogbo,ṣugbọn ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le yóo bọ́ sinu ìyọnu.

15. Ọba burúkú tí ó jọba lórí àwọn talaka,dàbí kinniun tí ń bú ramúramù,tabi ẹranko beari tí inú ń bí.

16. Ìkà, aninilára ni olórí tí kò ní òye,ṣugbọn ẹ̀mí ẹni tí ó bá kórìíra à ń jèrè lọ́nà èrú yóo gùn.

17. Bí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan bá ń da eniyan láàmú,yóo di ìsáǹsá ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀,kí ẹnikẹ́ni má ṣe ràn án lọ́wọ́.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 28