Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìwé Òwe 25:9-25 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Bí o bá ń bá aládùúgbò rẹ ṣe àríyànjiyànmá ṣe tú àṣírí ẹlòmíràn,

10. kí ẹni tí ó bá gbọ́ má baà dójútì ọ́,kí o má baà sọ ara rẹ lórúkọ.

11. Ọ̀rọ̀ tí a sọ lákòókò tí ó yẹdàbí ohun ọ̀ṣọ́ wúrà tí a gbé sinu àwo fadaka.

12. Ìbáwí ọlọ́gbọ́n dàbí òrùka wúrà,tabi ohun ọ̀ṣọ́ tí a fi wúrà ṣe,fún ẹni tí ó ní etí láti fi gbọ́.

13. Bí òtútù yìnyín nígbà ìkórè,bẹ́ẹ̀ ni olóòótọ́ iranṣẹ jẹ́, sí àwọn tí ó rán an,a máa fi ọkàn àwọn oluwa rẹ̀ balẹ̀.

14. Bí òjò tí ó ṣú dudu tí ó fẹ́ atẹ́gùn títíṣugbọn tí kò rọ̀,ni ẹni tí ó ń fọ́nnu láti fúnni lẹ́bùn,tí kò sì fúnni ní nǹkankan.

15. Pẹlu sùúrù, a lè yí aláṣẹ lọ́kàn padaọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́ sì lè fọ́ eegun.

16. Bí o bá rí oyin, lá a níwọ̀nba,má lá a ní àlájù, kí o má baà bì.

17. Má máa lọ sílé aládùúgbò rẹ lemọ́lemọ́,kí ọ̀rọ̀ rẹ má baà sú u, kí ó sì kórìíra rẹ.

18. Ẹni tí ó jẹ́rìí èké nípa aládùúgbò rẹ̀dàbí kùmọ̀ ọmọ ogun, tabi idà, tabi ọfà tí ó mú.

19. Igbẹkẹle ninu alaiṣootọ ní àkókò ìṣòro,dàbí eyín tí ń ro ni, tabi ẹsẹ̀ tí ó rọ́.

20. Bí ẹni tí a bọ́ṣọ rẹ̀ ninu òtútù,tabi tí a da ọtí kíkan sójú egbò rẹ̀,ni ẹni tí à ń kọrin fún ní àkókò tí inú rẹ̀ bàjẹ́.

21. Bí ebi bá ń pa ọ̀tá rẹ, fún un ní oúnjẹ jẹ,bí òùngbẹ bá ń gbẹ ẹ́, fún un ní omi mu.

22. Nípa bẹ́ẹ̀ o óo wa ẹ̀yinná lé e lórí,OLUWA yóo sì san ẹ̀san rere fún ọ.

23. Bí ẹ̀fúùfù ìhà àríwá tíí mú òjò wá,bẹ́ẹ̀ ni òfófó ṣíṣe máa ń fa kí a máa fi ojú burúkú woni.

24. Ó sàn kí á máa gbé kọ̀rọ̀ kan lókè àjà,ju pé kí eniyan máa bá oníjàngbọ̀n obinrin gbé ilé lọ.

25. Gẹ́gẹ́ bí omi tútù ti rí fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ,ni ìròyìn ayọ̀ láti ilẹ̀ òkèèrè rí.

Ka pipe ipin Ìwé Òwe 25