Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hosia 2:18-23 BIBELI MIMỌ (BM)

18. Nígbà náà ni n óo tìtorí tirẹ̀ bá àwọn ẹranko, àwọn ẹyẹ, ati àwọn nǹkan tí ń fi àyà fà lórí ilẹ̀ dá majẹmu, n óo sì mú ọfà, idà, ati ogun kúrò ní ilẹ̀ náà. N óo jẹ́ kí ẹ máa gbé ní alaafia ati ní àìléwu.

19. Ìwọ Israẹli, n óo sọ ọ́ di iyawo mi títí lae;n óo sọ ọ́ di iyawo mi lódodo ati lótìítọ́,ninu ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati àánú.

20. N óo sọ ọ́ di iyawo mi, lótìítọ́, o óo sì mọ̀ mí ní OLUWA.

21. OLUWA ní,“Ní ọjọ́ náà, n óo dáhùn adura ojú ọ̀run,ojú ọ̀run yó sì dáhùn adura ilẹ̀.

22. Ilẹ̀ yóo sì dáhùn adura ọkà, ati ti waini ati ti òróró.Àwọn náà óo sì dáhùn adura Jesireeli.

23. N óo fi ìdí àwọn eniyan mi múlẹ̀ ní ilẹ̀ náà,wọn yóo sì máa bí sí i.N óo ṣàánú ẹni tí a tí ń pè ní ‘Kò sí àánú’,n óo sì sọ fún ẹni tí a tí ń pè ní ‘Kì í ṣe eniyan mi’ pé eniyan mi ni;òun náà yóo sì dá mi lóhùn pé,‘Ìwọ ni Ọlọrun mi.’ ”

Ka pipe ipin Hosia 2