Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 21:5-17 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Wọ́n tẹ́ tabili, wọ́n sì tẹ́ aṣọ sílẹ̀wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu.Ariwo bá ta pé“Ẹ gbéra nílẹ̀, ẹ̀yin ológun!Ẹ fepo pa asà yín.”

6. Nítorí OLUWA wí fún mi pé:“Lọ fi aṣọ́nà ṣọ́ ojú ọ̀nà,kí ó máa kéde ohun tí ó bá rí.

7. Nígbà tí ó bá rí àwọn ẹlẹ́ṣintí wọn ń bọ̀ ní meji-meji, bí ó bá rí ití àwọn kan gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,tí àwọn kan gun ràkúnmí,kí ó fara balẹ̀ dáradára,kí ó dẹtísílẹ̀ dáradára.”

8. Ẹni tí ń ṣọ́nà kígbe pé:“OLUWA mi, lórí ilé-ìṣọ́ ni èmi í dúró sí lojoojumọ,níbi tí a fi mí ṣọ́, ni èmi í sì í wà ní òròòru.

9. Ẹ wò ó! Àwọn ẹlẹ́ṣin kan ń bọ̀,wọ́n fẹ̀gbẹ́kẹ̀gbẹ́ ní meji-meji!”“Ẹ gbọ́! Ìlú Babiloni ti wó! Ó ti wó!Pẹlu gbogbo àwọn oriṣa rẹ̀,ó ti wó lulẹ̀ patapata.”

10. Ẹ̀yin eniyan mi tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀,bí ẹni tẹ ọkà ní ibi ìpakà,ohun tí mo gbọ́ láti ọ̀dọ̀ OLUWA àwọn ọmọ ogun,Ọlọrun Israẹli, ní mò ń kéde fun yín yìí.

11. Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Edomu nìyí:Ẹnìkan ń pè mí láti SeiriÓ ní: “Aṣọ́nà, Òru ti rí o?Aṣọ́nà, àní òru ti rí?”

12. Aṣọ́nà bá dáhùn, ó ní:“Ilẹ̀ ń ṣú, ilẹ̀ sì ń mọ́.Bí ẹ bá tún fẹ́ bèèrè,ẹ pada wá, kí ẹ tún wá bèèrè.”

13. Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Arabia nìyí:Ninu igbó Arabia ni ẹ óo sùn, ẹ̀yin èrò ará Didani.

14. Ẹ bu omi wá fún ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ.Ẹ gbé oúnjẹ pàdé ẹni tí ń sá fógun, ẹ̀yin ará ilẹ̀ Tema.

15. Wọ́n ń sá fún idà,wọ́n sá fún idà lójú ogun.Wọ́n ń sá fún àwọn tafàtafà,wọ́n sá fún líle ogun.

16. OLUWA sọ fún mi pé, “Kí ó tó tó ọdún kan, ní ìwọ̀n ọdún alágbàṣe kan, gbogbo ògo Kedari yóo dópin;

17. díẹ̀ ni yóo sì kù ninu àwọn tafàtafà alágbára ọmọ Kedari; nítorí OLUWA Ọlọrun Israẹli ló sọ bẹ́ẹ̀.”

Ka pipe ipin Aisaya 21