Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Aisaya 19:10-21 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Àwọn eniyan pataki ilẹ̀ náà yóo di ẹni ilẹ̀,ìbànújẹ́ yóo sì bá àwọn alágbàṣe.

11. Òmùgọ̀ ni àwọn olórí wọn ní Soani;ìmọ̀ràn wèrè sì ni àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n ìgbìmọ̀ Farao ń fún eniyan.Báwo ni eniyan ṣe lè sọ fún Farao pé,“Ọmọ Ọlọ́gbọ́n eniyan ni mí,ọmọ àwọn ọba àtijọ́.”

12. Àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n rẹ dà?Níbo ni wọ́n wà kí wọ́n sọ fún ọ,kí wọ́n sì fi ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun pinnu láti ṣe sí Ijipti hàn ọ́.

13. Àwọn olórí wọn ní Soani ti di òmùgọ̀,àwọn olórí wọn ní Memfisi sì ti gba ẹ̀tàn;àwọn tí wọ́n jẹ́ òpómúléró ní ilẹ̀ Ijipti ti ṣi Ijipti lọ́nà.

14. OLUWA ti dá èdè-àìyedè sílẹ̀ láàrin wọn,wọ́n sì ti ṣi Ijipti lọ́nà ninu gbogbo ìṣe rẹ̀,bí ìgbà tí ọ̀mùtí bá ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n ninu èébì rẹ̀.

15. Kò sí nǹkankan tí ẹnìkan lè ṣe fún Ijipti,kì báà jẹ́ ọlọ́lá tabi mẹ̀kúnnù,kì báà jẹ́ eniyan pataki tabi ẹni tí kò jẹ́ nǹkan.

16. Tí ó bá di ìgbà náà, àwọn ará Ijipti yóo di obinrin. Wọn yóo máa gbọ̀n, fún ẹ̀rù, nígbà tí OLUWA àwọn ọmọ ogun bá gbá wọn mú.

17. Ilẹ̀ Juda yóo di ẹ̀rù fún àwọn ará Ijipti, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ yóo bẹ̀rù nítorí ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun ti pinnu láti ṣe sí Ijipti.

18. Tó bá di ìgbà náà, ìlú marun-un yóo wà ní ilẹ̀ Ijipti, tí wọn yóo máa sọ èdè Kenaani; wọ́n óo búra láti jẹ́ ti OLUWA àwọn ọmọ ogun.Orúkọ ọ̀kan ninu wọn yóo máa jẹ́ ìlú Oòrùn.

19. Tó bá di ìgbà náà, wọn yóo tẹ́ pẹpẹ kan fún OLUWA láàrin ilẹ̀ Ijipti, ọ̀wọ̀n OLUWA kan yóo sì wà lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ ààlà ilẹ̀ rẹ̀.

20. Yóo jẹ́ àmì ati ẹ̀rí fún OLUWA àwọn ọmọ ogun ní ilẹ̀ Ijipti. Nígbà tí wọ́n bá ké pe OLUWA nítorí àwọn aninilára, OLUWA yóo rán olùgbàlà tí yóo gbà wọ́n sí wọn.

21. OLUWA yóo sọ ara rẹ̀ di mímọ̀ fún àwọn ará Ijipti, wọn óo sì mọ OLUWA nígbà náà. Wọ́n yóo máa sin OLUWA pẹlu ẹbọ ati ẹbọ sísun; wọn óo jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún OLUWA, wọn yóo sì mú ẹ̀jẹ́ náà ṣẹ.

Ka pipe ipin Aisaya 19