Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 11:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ǹjẹ́ mo ní: Ọlọ́run ha ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù bí? Kí a má ri. Nítorí Ísírẹ́lì ni èmi pẹ̀lú, láti inú irú-ọmọ Ábúráhámù, ni ẹ̀yà Béńjámínì.

2. Ọlọ́run kò ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù ti ó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀. Tàbí ẹ̀yin kò mọ bí ìwé-mímọ́ ti wí ní ti Èlíjà? Bí ó ti ń bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run fún Ísírẹ́lì, wí pé:

3. “Olúwa, wọ́n ti pa àwọn wòlíì rẹ, wọn sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀; èmi nìkan soso ni ó sì kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi.”

4. Ṣùgbọ́n ìdáhùn wo ni Ọlọ́run fi fún un? “Mo ti paẹ̀ẹ́dẹ́gbàrin ènìyàn mọ́ sílẹ̀ fún ara mi, àwọn tí kò tẹ eékún ba fún Báálì.”

5. ẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni li àkókò ìsinsin yìí pẹ̀lú, apákan wà nípa ìyànfẹ́ ti ore-ọ̀fẹ́.

6. í ó bá sì ṣe pé nípa ti ore-ọ̀fẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti iṣẹ́ mọ́; àyàmọ̀bí ore-ọ̀fẹ́ kì í ṣe ore-ọ̀fẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe pe nípa ti iṣẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti ore-ọ̀fẹ́ mọ́; àyàmọ̀bí iṣẹ́ kì í ṣe iṣẹ́ mọ́.

7. Kí ha ni? Ohun tí Isírẹ́lì ń wá kiri, òun náà ni kò rí; ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìyànfẹ́ ti rí i, a sì ṣé àyà àwọn ìyókù le.

8. Èyí ni ìwé Mímọ́ ń wí nígbà tí ó sọ pé:“Ọlọ́run ti fi oorun kùn wọ́n,ó sì dí ojú àti etí wọn,wọn kò sì le ní ìmọ̀ Kírísítì nígbà tí a bá ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ síwọn.Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ó sì rí títí di ọjọ́ òní.”

9. Ohun kan náà yìí ni Dáfídì ọba sọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé:“Kí oúnjẹ àti àwọn nǹkan mèremère wọn tàn wọ́n,láti rò pé wọ́n rí ojú rere Ọlọ́run.Jẹ́ kí àwọn nǹkan wọ̀nyí padà dojú ìjà kọ wọ́n,kí a bá à lè fi òtítọ́ wó wọn túútúú.

Ka pipe ipin Róòmù 11