Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 11:10-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Èyí ni ẹni tí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé:“ ‘Èmi yóò rán ìránṣẹ́ mi ṣíwájú rẹ,ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’

11. Lóòótọ̀ ni mó wí fún yín, nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí ẹni tí ó tí í dìde tí ó ga ju Jòhánù onítẹ̀bọmi lọ, síbẹ̀ ẹni tí ó kéré jù ní ìjọba ọ̀run ni ó pọ̀ jù ú lọ.

12. Láti ìgbà ọjọ́ Jòhánù onítẹ̀bọmi títí di àkókò yìí ni ìjọba ọ̀run ti di àfagbárawọ̀, àwọn alágbára ló ń fi ipá gbà á.

13. Nítorí náà gbogbo òfin àti wòlíì ni ó wí tẹ́lẹ̀ kí Jòhánù kí ó tó dé.

14. Bí ẹ̀yin yóò bá gbà á, èyí ni Èlíjà tó ń bọ̀ wá.

15. Ẹni tí ó bá ní etí, kí ó gbọ́

16. “Kí ni èmi ìbá fi ìran yìí wé? Ó dàbí àwọn ọmọ kékéré tí ń jókòó ní ọjà tí wọ́n sì ń ké pe àwọn ẹlẹ́gbẹ́ wọn:

17. “ ‘Àwa ń fun fèrè fún yín,ẹ̀yin kò jó;àwa kọrin ọ̀fọ̀ẹ̀yin kò káàánú.’

18. Nítorí Jòhánù wá kò bá a yín jẹ bẹ́ẹ̀ ni kò mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù.’

19. Ọmọ ènìyàn wá bá a yín jẹun, ó sì bá yin mu, wọ́n wí pé, ọ̀jẹun àti ọ̀mùtì; ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́sẹ̀, ṣùgbọ́n a dá ọgbọ́n láre nípa ìṣe rẹ̀.”

20. Nígbà náà ni Jésù bẹ̀rẹ̀ sí í bá ìlú tí ó ti ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ wí, nítorí wọn kò ìronúpìwàdà.

21. Ó wí pé, “Ègbé ni fún ìwọ Kórásínì, ègbé ni fún ìwọ Bẹtisáídà! Ìbá ṣe pé a ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu tí a se nínú yín ní Tírè àti Sídónì, àwọn ènìyàn wọn ìbá ti ronúpìwàdà tipẹ́ nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.

22. Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Tírè àti Sídónì ní ọjọ́ ìdájọ́ jù fún yín.

Ka pipe ipin Mátíù 11