Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 10:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jésù sì pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá sí ọ̀dọ̀; ó fún wọn ní àṣẹ láti lé ẹ̀mí àìmọ́ jáde àti láti ṣe ìwòsàn àrùn àti àìsàn gbogbo.

2. Orúkọ àwọn àpósítélì méjèèjìlá náà ni wọ̀nyí: ẹni àkọ́kọ́ ni Símónì ẹni ti a ń pè ni Pétérù àti arákùnrin rẹ̀ Ańdérù, Jákọ́bù ọmọ Sébédè àti arákùnrin rẹ̀ Jòhánù.

3. Fílípì àti Bátólómíù; Tómásì àti Mátíù agbowó òde; Jákọ́bù ọmọ Álíféù àti Tádéù;

4. Símónì ọmọ ẹgbẹ́ Sílíọ́tì, Júdásì Ísíkáríọ́tù, ẹni tí ó da Jésù.

5. Jésù ran àwọn méjèèjìla yìí jáde, pẹ̀lú àṣẹ báyìí pé: “Ẹ má ṣe lọ sì àárín àwọn aláìkọlà tàbí wọ̀ èyíkèyìí ìlú àwọn ará Samáríà

6. Ẹ kúkú tọ̀ àwọn àgùntàn ilé Ísírẹ́lì tí ó nù lọ.

Ka pipe ipin Mátíù 10