Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 9:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòtọ́ ni mo wí fún un yín àwọn mìíràn wa nínú àwọn tó dúró níhìnín yìí, tí kì yóò tọ́ ikú wò, títi yóò fi rí ìjọba Ọlọ́run tí yóò fi dé pẹ̀lú agbára.”

2. Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́fà tí Jésù sọ̀rọ̀ yìí, Jésù mú Pétérù, Jákọ́bù àti Jòhánù lọ sí orí òkè gíga ní apákan. Kò sí ẹlòmíràn pẹ̀lú wọn, ara rẹ̀ sì yípadà níwájú wọn.

3. Aṣọ rẹ̀ sì di dídán, ó sì funfun gbòò, tí alágbàfọ̀ kan láyé kò lè sọ di funfun bẹ́ẹ̀.

4. Nígbà náà ni Èlíjà àti Mósè farahàn fún wọn, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ pẹ̀lú Jésù.

5. Pétérù sì wí fún Jesù pé, “Rábì, ó dára fún wa láti máa gbé níhìnín, si jẹ́ kí a pa àgọ́ mẹ́ta, ọ̀kan fun ọ, ọ̀kan fún Mósè, àti ọ̀kan fún Èlíjà.”

6. Nítorí òun kò mọ ohun tí òun ìba sọ, nítorí ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.

7. Ìkuukuu kan sì bò wọ́n, ohùn kan sì ti inú ìkúùkù náà wá wí pé: “Èyí ni àyànfẹ ọmọ mi: Ẹ máa gbọ́ ti rẹ̀!”

8. Lójijì, wọ́n wo àyíká wọn, wọn kò sì rí ẹnìkan kan mọ́, bí kò ṣe Jésù nìkan ṣoṣo ni ó sì wà pẹ̀lú wọn.

9. Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, Jésù kìlọ̀ fún wọn kí wọ́n má ṣe sọ ohun tí wọ́n ti rí fún ẹnikẹ́ni títí Ọmọ-Ènìyàn yóò fi jíǹde kúrò nínú òkú.

Ka pipe ipin Máàkù 9