Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 8:5-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Jésù béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ìsù búrẹ́dì mélòó lẹ ní lọ́wọ́?”Wọ́n fèsì pé, “isu búrédì méje.”

6. Nítori náà, ó pàsẹ fún àwọn ènìyàn náà láti jókòó lórí ilẹ̀. Ó sì mú odindi búrédì méje náà, ó dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, ó sì bù wọ́n sí wẹ́wẹ́, ó pín wọ́n fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti gbé ka iwájú àwọn ènìyàn, wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.

7. Wọ́n rí àwọn ẹja wẹ́wẹ́ díẹ̀ pẹ̀lú. Jésù tún dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún ìpèsè náà, ó sì pàṣẹ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti pín wọ́n fún àwọn ènìyàn náà.

8. Gbogbo ọ̀pọ̀ ènìyàn náà ló jẹ àjẹyó àti àjẹtẹ́rùn. Lẹ́yìn èyí wọ́n kó àjẹkù ti ó kù jọ, agbọ̀n méje sì kún.

9. Àwọn tí ó jẹ ẹ́ tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́rin (4000) ènìyàn, ó sì rán wọn lọ.

10. Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, lẹ́yìn èyí, Jésù wọ inú ọkọ̀ ojú-omi pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì gúnlẹ̀ sí agbègbè Dálímánútà.

11. Àwọn Farisí tọ Jésù wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí bèèrè ìbéèrè lọ́wọ́ rẹ̀. Láti dán an wò, wọ̀n bèèrè fún àmì láti ọ̀run.

Ka pipe ipin Máàkù 8