Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Lúùkù 6:42-47 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

42. Tàbí ìwọ ó ti ṣe lè wí fún arákùnrin rẹ pé, ‘Arákùnrin, jẹ́ kí èmi yọ èérún igi tí ń bẹ lójú rẹ,’ nígbà tí ìwọ tìkararẹ kò kíyèsí ìtì igi tí ń bẹ lójú rẹ? Ìwọ àgàbàgebè, kọ́kọ́ yọ ìtí igi jáde kúrò lójú ara rẹ ná, nígbà náà ni ìwọ ó sì tó ríran gbangba láti yọ èérún igi tí ń bẹ lójú arákùnrin rẹ kúrò.

43. “Nítorí igi rere kì í so èso búburú; bẹ́ẹ̀ ni igi búburú kì í so èso rere.

44. Olúkúlùkù igi ni a ń fi èso rẹ̀ mọ̀ ọn; nítorí lórí ẹ̀gún òṣùṣú, ènìyàn kì í ká èṣo ọ̀pọ̀tọ́ bẹ́ẹ̀ ni lórí ẹ̀gún ọ̀gàn a kì í ká èṣo àjàrà.

45. Ènìyàn rere láti inú ìsúra rere ọkàn rẹ̀ ní mú ohun rere jáde wá; àti ènìyàn búburú láti inú ìṣúra búburú ọkàn rẹ̀ ní í mú ohun búburú jáde wá: nítorí ohun tí ó wà nínú ọkàn ni ẹnu rẹ̀ ń sọ.

46. “Nítorí náà, èéṣe tí ẹ̀yin ń pè mí ní, ‘Olúwa, Olúwa,’ tí ẹ̀yin kò sì ṣe ohun tí mo wí?

47. Ẹnikẹ́ni tí ó tọ̀ mí wá, tí ó sì ń gbọ́ mi, tí ó sì ń ṣe é, èmi yóò fi ẹni tí ó jọ hàn yín;

Ka pipe ipin Lúùkù 6