36. “Nínú àwọn mẹ́tẹ̀èta wọ̀nyí, tani ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
37. Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un.”Jésù sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
38. Ó sì se, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Mátà sì gbà á sí ilé rẹ̀.
39. Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Màríà tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹṣẹ̀ Jésù, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.