Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 9:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Bí ó sì ti ń kọjá lọ, ó rí ọkùnrin kan tí ó fọ́jú láti ìgbà ìbí rẹ̀ wá.

2. Àwọn Ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ sì bi í léèrè, pé, “Olùkọ́, ta ní ó dẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin yìí tàbí àwọn òbí rẹ̀, tí a fi bí i ní afọ́jú?”

3. Jésù dáhùn pé, “Kì í ṣe nítorí pé ọkùnrin yìí dẹ́ṣẹ̀, tàbí àwọn òbí rẹ̀: ṣùgbọ́n kí a baà lè fi iṣẹ́ Ọlọ́run hàn lara rẹ̀.

4. Àwa ní láti ṣe iṣẹ́ ẹni tí ó rán mi, níwọ̀n ìgbà tí ó ba ti jẹ́ ọ̀sán: òru ń bọ̀ wá nígbà tí ẹnìkan kì yóò lè ṣe iṣẹ́.

5. Níwọ̀n ìgbà tí mo wà láàyè, èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé.”

6. Nígbà tí ó ti wí bẹ́ẹ̀ tan, ó tutọ́ sílẹ̀, ó sì fi itọ́ náà ṣe amọ̀, ó sì fi amọ̀ náà pa ojú afọ́jú náà.

7. Ó sì wí fún un pé, “Lọ wẹ̀ nínú adágún Sílóámù!” (Ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ yìí ni “rán”). Nítorí náà ó gba ọ̀nà rẹ̀ lọ, ó wẹ̀, ó sì dé, ó ń ríran.

8. Ǹjẹ́ àwọn aládúgbò àti àwọn tí ó rí i nígbà àtijọ́ pé alágbe ni ó jẹ́, wí pé, “Ẹni tí ó ti ń jókòó ṣagbe kọ́ yìí?”

9. Àwọn kan wí pé òun ni.Àwọn elòmíràn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ó jọ ọ́ ni.”Ṣùgbọ́n òun wí pé, “Èmi ni.”

Ka pipe ipin Jòhánù 9