Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jòhánù 11:51-57 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

51. Kì í ṣe fún ara rẹ̀ ni ó sọ èyí ṣùgbọ́n bí ó ti jẹ́ olórí àlùfáà ní ọdún náà, ó sọtẹ́lẹ̀ pé, Jésù yóò kú fún orílẹ̀-èdè náà:

52. Kì sì í ṣe kìkì fún orílẹ̀-èdè náà nìkan, ṣùgbọ́n bí ó ti jẹ́ olórí àlùfáà ní ọdún náà, ó sọtẹ́lẹ̀ pé, Jésù yóò kú fún orílẹ̀-èdè náà:

53. Nítorí náà, láti ọjọ́ náà lọ ni wọ́n ti jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.

54. Nítorí náà Jésù kò rìn ní gbangba láàárin àwọn Júù mọ́; ṣùgbọ́n ó ti ibẹ̀ lọ sí ìgbéríko kan tí ó sún mọ́ ihà, sí ìlú ńlá kan tí a ń pè ní Éfúráímù, níbẹ̀ ni ó sì wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.

55. Àjọ ìrékọjá àwọn Júù sì sún mọ́ etílé: ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti ìgbéríko sì gòkè lọ sí Jérúsálẹ́mù ṣáájú ìrékọjá, láti ya ara wọn sí mímọ́.

56. Nígbà náà ni wọ́n ń wá Jésù, wọ́n sì ń bá ara wọn sọ̀, bí wọ́n ti dúró ní tẹ́mpílì, wí pé, “Ẹ̀yin ti rò ó sí? Pé kì yóò wá sí àjọ?”

57. Ǹjẹ́ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisí ti pàṣẹ pé bí ẹnìkan bá mọ ibi tí ó gbé wà, kí ó fi í hàn, kí wọn baà lè mú un.

Ka pipe ipin Jòhánù 11