47. Nígbà náà ni àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisí pe ìgbìmọ̀ jọ, wọ́n sì wí pé,“Kínni àwa ń ṣe? Nítorí ọkùnrin yìí ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì.
48. Bí àwa bá fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀, gbogbo ènìyàn ni yóò gbà á gbọ́: àwọn ará Rómù yóò sì wá gba ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè wa pẹ̀lú.”
49. Ṣùgbọ́n Káyáfà, ọ̀kan nínú wọn, ẹni tí í ṣe olórí àlùfáà ní ọdún náà, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin kò mọ ohunkóhun rárá!
50. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì ronú pé, ó sàǹfàní fún wa, kí ènìyàn kan kú fún àwọn ènìyàn kí gbogbo orílẹ̀-èdè má baà ṣègbé.”
51. Kì í ṣe fún ara rẹ̀ ni ó sọ èyí ṣùgbọ́n bí ó ti jẹ́ olórí àlùfáà ní ọdún náà, ó sọtẹ́lẹ̀ pé, Jésù yóò kú fún orílẹ̀-èdè náà:
52. Kì sì í ṣe kìkì fún orílẹ̀-èdè náà nìkan, ṣùgbọ́n bí ó ti jẹ́ olórí àlùfáà ní ọdún náà, ó sọtẹ́lẹ̀ pé, Jésù yóò kú fún orílẹ̀-èdè náà:
53. Nítorí náà, láti ọjọ́ náà lọ ni wọ́n ti jọ gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
54. Nítorí náà Jésù kò rìn ní gbangba láàárin àwọn Júù mọ́; ṣùgbọ́n ó ti ibẹ̀ lọ sí ìgbéríko kan tí ó sún mọ́ ihà, sí ìlú ńlá kan tí a ń pè ní Éfúráímù, níbẹ̀ ni ó sì wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
55. Àjọ ìrékọjá àwọn Júù sì sún mọ́ etílé: ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti ìgbéríko sì gòkè lọ sí Jérúsálẹ́mù ṣáájú ìrékọjá, láti ya ara wọn sí mímọ́.