Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 7:5-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Láti inú ẹ̀yà Júdà a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.Láti inú ẹ̀yà Reubẹ́nì a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.Láti inú ẹ̀yà Gádì a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.

6. Láti inú ẹ̀yà Ásérì a fi èdídí sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.Láti inú ẹ̀yà Nefítalímù a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.Láti inú ẹ̀yà Mánásè a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.

7. Láti inú ẹ̀yà Simeónì a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.Láti inú ẹ̀yà Léfì a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.Láti inú ẹ̀yà Ísakárì a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.

8. Láti inú ẹ̀yà Sebulúnì a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.Láti inú ẹ̀yà Jósẹ́fù a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.Láti inú ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá mẹ́fà.

9. Lẹ́yìn náà, mo ri, sì kíyèsí i, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn tí ẹnikẹ́ni kò lè kà, láti inú orílẹ̀-èdè gbogbo, àti ẹ̀yà, àti ènìyàn, àti láti inú èdè gbogbo wá, wọn dúró níwájú ìtẹ́, àti níwájú Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà, a wọ̀ wọ́n ni aṣọ funfun, imọ̀ ọ̀pẹ si ń bẹ ni ọwọ́ wọn.

Ka pipe ipin Ìfihàn 7