Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 19:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí mo gbọ́ ohùn ńlá ní ọ̀run bí ẹni pé tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, ń wí pé:“Halelúyà!Ti Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà, àti ọlá agbára,

2. nítorí òtítọ́ àti òdodo ni ìdájọ́ rẹ̀.Nítorí o ti ṣe ìdájọ́ àgbèrè ńlá a nì,tí o fi àgbèrè rẹ̀ ba ilẹ́ ayé jẹ́, ó sì ti gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀ náà.”

3. Àti lẹ́ẹ̀kejì wọ́n wí pé:“Halelúyà!Èéfín rẹ̀ sì gòkè lọ láé àti láéláé.”

4. Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún nì, àti àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin nì sì wólẹ, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run tí ó jókòó lórí ìtẹ́, wí pé:“Àmín, Halelúyà!”

5. Ohùn kan sì ti ibi ìtẹ́ náà jáde wá, wí pé:“Ẹ máa yin Ọlọ́run wa,ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo,ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù rẹ̀,àti èwe àti àgbà!”

Ka pipe ipin Ìfihàn 19