Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 10:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Mó sì rí ańgẹ́lì mìíràn alágbára ò ń ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, a fi awọsànmà wọ̀ ọ́ ni aṣọ; òṣùmàrè sì ń bẹ ní orí rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dàbí òòrùn, àti ẹṣẹ̀ rẹ̀ bí ọ̀wọ́n iná.

2. Ó sì ní ìwé kékeré kan tí a sí ní owọ́ rẹ̀; ó sì fi ẹṣẹ rẹ̀ ọ̀tún lé òkun, àti ẹṣẹ̀ rẹ̀ òsì lé ilẹ̀.

3. Ó sì ké lóhùn rara, bí ìgbà tí kìnnìún bá bú ramúramù. Nígbà tí ó sì ké, àwọn àrá méje náà fọhùn.

4. Nígbà tí àwọn àrá méje fọhùn, mo múra àti kọ̀wé: mo sì gbọ ohùn láti ọ̀run wá ń wí fún pé, “Fi èdìdì di ohun tí àwọn àrá méje náà sọ, má sì ṣe kọ wọ́n sílẹ̀.”

5. Ańgẹ́lì náà tí mo rí tí ó dúró lórí òkun àti lórí ilẹ̀, sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sí òkè ọ̀run:

Ka pipe ipin Ìfihàn 10