Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7:5-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Kò sí fún un ni ìní kan, àní tó bi ìwọ̀n ààyè ẹṣẹ̀ kan. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run se ìlérí fún pé, òun yóò fi ilẹ̀-ìní náà fún un àti fún àwọn irú ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí kò tí ì ní ọmọ.

6. Ọlọ́run sì sọ báyìí pé: ‘Irú-ọmọ rẹ̀ yóò ṣe àtìpó ni ilẹ̀ àjèjì; wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú ni irínwó ọdún.’

7. Ọlọ́run wí pé, ‘Orílẹ̀-èdè náà tí wọn ó ṣe ẹrú fún ni èmi ó dá lẹ́jọ́; lẹ́yìn náà ni wọn ó sì wá sìn mí níhín yìí.’

8. Ó sì fún Ábúráhámù ni májẹ̀mú ìkọlà. Ábúráhámù bí Ísáákì, ó kọ ọ́ ní ilà-abẹ́ ni ijọ́ kẹjọ tí ó bí i. Ísáákì sí bí Jákọ́bù, Jákọ́bù sì bí àwọn baba ńlá méjìlá.

9. “Àwọn baba ńlá sí ṣe ìlara Jósẹ́fù, wọ́n sì tà á sí Íjíbítì; ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀,

10. ó sì yọ ọ́ kúrò nínú ìpọ́njú rẹ̀ gbogbo. Ó sì fún Jósẹ́fù ní ọgbọ́n, ó sì mú kí ó rí ojúrere Fáráò ọba Íjíbítì; òun sì fi jẹ baálẹ̀ Íjíbítì àti gbogbo ilé rẹ̀.

11. “Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Íjíbítì àti ni Kénánì, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7