Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7:25-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Mósè rò bí àwọn ará òun mọ̀ pé Ọlọ́run yóò ti ọwọ́ òun gbà wọn; ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀.

26. Ní ọjọ́ kejì Mósè yọ sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì méjì bí wọ́n ti ń jà. Òun ì bá sí parí rẹ̀ fún wọn. Ó wí pé, ‘Ènìyàn mi, ará ni ẹ̀yin; è é ṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣe ohun tí kò tọ́ sí ara yín?’

27. “Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fínràn sí ẹnìkejì rẹ̀ tì Mósè sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó wí pé, ‘Ta ni ó fi ọ jẹ olórí àti onídàjọ́ wa?

28. Àbí ìwọ ń fẹ́ pa mi gẹ́gẹ́ bí o ti pa ará Íjíbítì lánàá?’

29. Mósè sì sá nítorí ọ̀rọ̀ yìí, ó sì wa ṣe àtìpó ni ilẹ̀ Mídíànì, níbi tí ó gbé bí ọmọ méjì.

30. “Nígbà tí ogójì ọdún sì pé, ańgẹ́lì Olúwa fara hàn Mósè ní ijù, ní òkè Sínáì, nínú ọ̀wọ́ iná ìgbẹ́.

31. Nígbà tí Mósè sì rí i, ẹnu yà á sí ìran náà; nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti wò ó fín, ohùn Olúwa kọ sí i,

32. Wí pé ‘Èmi ni Ọlọ́run àwọn baba rẹ, Ọlọ́run Ábúráhámù àti Ọlọ́run Ísáákì, àti Ọlọ́run Jákọ́bù,’ Mósè sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù, kò sì dàṣà láti wò ó mọ́.

33. “Olúwa sì wí fún un pé, ‘Tú bátà rẹ kúrò ni ẹsẹ̀ rẹ, nitorí ibi tí ìwọ gbé dúró sí yìí ilẹ̀ mímọ́ ni.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 7