Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 5:37-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

37. Lẹ́yìn ọkùnrin yìí ni Júdà ti Gálílì dìde ni àkókò kíka àwọn ènìyàn, ó sì fa ẹni púpọ̀ lẹ́yìn rẹ̀; òun pẹ̀lú ṣègbé; àti gbogbo iye àwọn tí ó gba tirẹ̀ ni a fọ́nká.

38. Ǹjẹ́ èmi wí fún un yín nísinsin yìí, Ẹ gáfárà fún àwọn ọkùnrin wọ̀nyí, kí ẹ sí fi wọn sílẹ̀, nítorí bí ìmọ̀ tàbí iṣẹ́ yìí bá jẹ́ ti ènìyàn, a ó bì í ṣúbu.

39. Ṣùgbọ́n bí ti Ọlọ́run bá ní, ẹ̀yin kì yóò lè bì í ṣúbu; kí ó má ba à jẹ́ pé, a rí yín bí ẹni tí ń bá Ọlọ́run jà”

40. Wọ́n sì gbà ìmọ̀ràn rẹ̀. Wọn pe àwọn àpósítélì wọlé, wọ́n lù wọ́n. Wọn sí kìlọ̀ fún wọn pé kí wọn má ṣe sọ̀rọ̀ ni orúkọ Jésù mọ́, wọ́n sì jọ̀wọ́ wọn sílẹ̀ lọ.

41. Nítorí náà wọn sì lọ kúrò níwájú àjọ ìgbìmọ̀; wọn ń yọ̀ nítorí tí a kà wọ́n yẹ láti jìyà nítorí orúkọ rẹ̀.

42. Ní ojoojúmọ́ nínú tẹ́ḿpílì àti ni ojúlé dé ojúlé, wọn kò dẹ́kùn kíkọ́ni àti láti wàásù ìyìn rere náà pé Jésù ni Kírísítì

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 5