Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 26:8-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Èéṣe tí ẹ̀yin fi rò o sí ohun tí a kò lè gbàgbọ́ bí Ọlọ́run bá jí òkú dìde?

9. “Èmi tilẹ̀ rò nínú ará mi nítòótọ́ pé, ó yẹ ki èmi ṣe ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ ohun lòdì sí orúkọ Jésù tí Násárétì.

10. Èyi ni mo sì ṣe ni Jerúsálémù. Pẹ̀lú àṣẹ tí mo tí gba lọ́dọ̀ àwọn olórí àlùfáà, mo sọ àwọn púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn mímọ́ sí inú túbú, nígbà tí wọ́n sí ń pa wọ́n, mo ní ohùn sí i.

11. Nígbà púpọ̀ ni mo ń fi ìyà jẹ wọ́n láti inú ṣínágọ́gù dé inú ṣínágọ́gù, mo ń fi tipá mú wọn láti sọ ọ̀rọ̀-òdì. Mo sọ̀rọ̀ lòdì ṣí wọn gidigidi, kódà mo wá wọn lọ sí ìlú àjèjì láti ṣe inúnibíni sí wọn.

12. “Nínú irú ìrìnàjò yìí ní mo ń bá lọ sí Dámásíkù pẹ̀lú ọlá àti àṣẹ ikọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olórí àlùfáà.

13. Ni ọ̀ṣángangan, ìwọ ọba, bí mo ti wà ní ojú ọ̀nà, mo rí ìmọ́lẹ̀ kan láti ọ̀run wá, tí ó mọ́lẹ̀ ju òòrùn lọ, ó mọ́lẹ̀ yí mi ká, àti àwọn tí ń bá mi lọ sì àjò.

14. Gbogbo wa sì ṣubú lulẹ̀, mo gbọ́ ohùn tí ń fọ sì mi ni èdè Hébérù pé, ‘Ṣọ́ọ̀lù, Ṣọ́ọ̀lù! Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe inúnibíni ṣí mi? Ohun ìrora ní fún ọ láti tàpá sí ẹ̀gún!’

15. “Èmi sì wí pé, ‘Ìwọ ta ni, Olúwa?’“Olúwa sì wí pé, ‘Èmi ni Jésù tí ìwọ ń ṣe inúnibíni sí.

16. Ṣùgbọ́n dìde, kí o sí fi ẹṣẹ̀ rẹ tẹlẹ̀: nítorí èyí ni mo ṣe farahàn ọ́ láti yàn ọ́ ní ìránṣẹ́ àti ẹlẹ́rìí, fún ohun wọ̀nyí tí ìwọ tí rí nípa mi, àti àwọn ohun tí èmi yóò fí ara hàn fún ọ:

17. Èmi yóò gbà ọ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn rẹ àti lọ́wọ́ àwọn Kèfèrì. Èmi rán ọ ṣí wọn nísìnsìn yìí

18. láti là wọ́n lójú, kí wọn lè yípadà kúrò nínú òkùnkùn sí ìmọ́lẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ agbára Sátanì ṣí Ọlọ́run, kí wọn lè gba ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀, àti ogún pẹ̀lú àwọn tí a sọ di mímọ̀ nípa ìgbàgbọ́ nínú mi.’

19. “Nítorí náà, Àgírípà ọba, èmi kò ṣe àìgbọ́ràn sì ìran ọ̀run náà.

20. Ṣùgbọ́n mo kọ́kọ́ sọ fún àwọn tí ó wà ní Dámásíkù, àti ní Jerúsálémù, àti já gbogbo ilẹ Jùdíà, àti fún àwọn Kèfèrì, kí wọn ronúpìwàdà, kí wọ́n sì yípadà sí Ọlọ́run, kí wọn máa ṣe iṣẹ́ tí ó yẹ sì ìrònúpìwadà.

21. Nítorí nǹkan wọ̀nyí ni àwọn Júù ṣe gbá mi mú nínú tẹ́ḿpílì, tí wọ́n sì ń fẹ́ pá mí.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 26