Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 24:2-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Nígbà tí a sí tí pè Pọ́ọ̀lù jáde, Tátúlù gbé ẹjọ́ rẹ̀ kalẹ̀ níwájú Fẹ́líkísì ó wí pé: “Àwa ti wà ní àlàáfíà ní abẹ́ ìjọba rẹ lá ìgbà pípẹ́ wá, àti pé ìfojúsù rẹ ti mú àyípadà rere bá orílẹ̀-èdè yìí.

3. Ní ibi gbogbo àti ní ọ̀nà gbogbo, Fẹ́líkísì ọlọ́lá jùlọ, ní àwa ń tẹ́wọ́gbà á pẹ̀lú ọpẹ́ gbogbo.

4. Ṣùgbọ́n kí èmi má baa dá ọ dúró pẹ́ títí, mo bẹ̀ ọ́ kí o fi ìyọ́nú rẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ díẹ̀ lẹ́nu wa.

5. “Nítorí àwa rí ọkùnrin yìí, ó jẹ́ oníjàngbàn ènìyàn, ẹni tí ó ń dá rúkèrúdò ṣílẹ̀ láàrin gbogbo àwọn Júù tí ó wà ní gbogbo ayé. Òun ni aṣáájú búburú kan nínú ẹ̀yà àwọn Násárénè:

6. Ẹni tí ó gbìyànjú láti ba tẹ́ḿpílì jẹ́: ṣùgbọ́n àwa gbá a mú àwa sí fẹ báa ṣe ẹjọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin wa.

7. Ṣùgbọ́n Lísíà olórí ogun dé, ó fì agbára ńlá gbà á lọ́wọ́ wa:

8. Nígbà tí ìwọ fúnrarẹ bá wádìí ọ̀rọ̀ fínní fínni lẹ́nu rẹ̀, ìwọ ó lè ní òye òtítọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí àwa fi ẹ̀ṣùn rẹ̀ kàn án.”

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 24