Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 24:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn ọjọ́ márùn-ún Ananíyà olórí àlúfáà náà sọkalẹ̀ lọ pẹ̀lú àwọn alàgbà àti ẹnìkan, Tátúlù agbẹjọ́rò, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ẹjọ́ Pọ́ọ̀lù fún baálẹ̀.

2. Nígbà tí a sí tí pè Pọ́ọ̀lù jáde, Tátúlù gbé ẹjọ́ rẹ̀ kalẹ̀ níwájú Fẹ́líkísì ó wí pé: “Àwa ti wà ní àlàáfíà ní abẹ́ ìjọba rẹ lá ìgbà pípẹ́ wá, àti pé ìfojúsù rẹ ti mú àyípadà rere bá orílẹ̀-èdè yìí.

3. Ní ibi gbogbo àti ní ọ̀nà gbogbo, Fẹ́líkísì ọlọ́lá jùlọ, ní àwa ń tẹ́wọ́gbà á pẹ̀lú ọpẹ́ gbogbo.

4. Ṣùgbọ́n kí èmi má baa dá ọ dúró pẹ́ títí, mo bẹ̀ ọ́ kí o fi ìyọ́nú rẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ díẹ̀ lẹ́nu wa.

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 24