Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìṣe Àwọn Àpósítélì 18:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yin nǹkan wọ̀nyí, Pọ́ọ̀lù jáde kúrò ni Aténì, lọ sí Kọ́ríńtì;

2. Ó sì rí Júù kan tí a ń pè ní Àkúílà, tí a bí ni Pọ́ńtù, tí ó ti Ìtalì dé ní lọ́ọ́lọ́ọ́, pẹ̀lú Pírísíkílà aya rẹ̀; nítorí tí Kíláúdíù pàsẹ pé, kí gbogbo àwọn Júù jáde kúrò ní Róòmù. Ó sì tọ̀ wọ́n lọ láti rí wọn.

3. Nítorí tí òun náà jẹ́ onísẹ̀-ọwọ́ kan náà, ó bá wọn jókòó, ó sì nṣíṣẹ́: nítorí àgọ́ pípa ni iṣẹ́-ọwọ́ wọn.

4. Ó sì ń fọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀ fún wọn nínú ṣínágógù lọ́jọjọ́ ìsinmi, ó sì ń yí àwọn Júù àti àwọn Gíríkì lọ́kàn padà.

5. Nígbà tí Sílà àti Tímótíù sì tí Makedóníà wá, ọ̀rọ̀ náà ká Pọ́ọ̀lù lára, ó ń fi hàn fún àwọn Júù pé, Jésù ni Kírísítì náà.

6. Nígbà tí wọ́n sì sàtakò rẹ̀, tí wọ́n sì sọ̀rọ̀-òdì, ó gbọ́n aṣọ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀jẹ̀ yin ń bẹ lórí ara yin; ọrùn èmi mọ́: láti ìsinsìnyìí lọ, èmi yóò tọ àwọn aláìkọlà lọ.”

7. Ó sì lọ kúrò níbẹ, ó wọ ile ọkùnrin kan tí a ń pé ní Títù Júsù, ẹni tí o ń sin Ọlọ́run; ilé rẹ̀ sì wà lẹ́gbẹ̀ Sínágógù tímọ́tímọ́.

8. Kírísípù, olórí ṣínágọ́gù, sì gba Olúwa gbọ́ pẹ̀lú gbogbo ilé rẹ̀: àti ọ̀pọ̀ nínú àwọn ara Kọ́ríńtì, nígbà tí wọ́n gbọ́, wọ́n gbàgbọ́, a sì bamitíìsì wọn.

9. Olúwa sì sọ fún Pọ́ọ̀lù lóru ni ojúran pé, “Má bẹ̀rù, sá máa sọ, má sì se pá ẹnu rẹ̀ mọ́:

10. Nítorí tí èmí wà pẹ̀lú rẹ, kò sì sí ẹni tí yóò dìde sí ọ láti pa ọ lára: nítorí mo ní ènìyàn púpọ̀ ni ìlú yìí.”

Ka pipe ipin Ìṣe Àwọn Àpósítélì 18