Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Fílípì 1:21-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Nítorí, níti èmi, láti wa láàyè jẹ́ Kírísítì, láti kú jẹ́ èrè.

22. Ṣùgbọ́n bí èmi bá sì wà láàyè nínú ara, èyí yóò jásí èrè fún iṣẹ́ mi. Síbẹ̀, kíni èmí yóò yàn? Èmi kò mọ̀?

23. Mo wà ní agbede méjì. Mo fẹ́ràn láti wà pẹ̀lú Kírísítì, èyí tí ó dára jùlọ.

24. Ṣùgbọ́n ó ṣe iyebíye fún yín kí èmi kí ó wà nínú ara.

25. Bí èyí sì ti dá mi lójú, mo mọ̀ pé èmi ó dúró, èmi ó sì máa wà pẹ̀lú yín fún ìtẹ̀síwájú àti ayọ̀ yín nínú ìgbàgbọ́,

26. kí ìbádàpọ̀ mi pẹ̀lú yín lẹ́ẹ̀kan si le ru ayọ̀ yín sókè nínú Kírísítì nítorí mi.

27. Ohun tó wù kí ó ṣẹlẹ̀, ẹ jẹ́ kí iṣẹ́ yín wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyìnrere Kírísítì. pé yálà bí mo tilẹ̀ wá wò yín, tàbí bí èmi kò wá, kí èmi lè máa gbúròó bí ẹ ti ń ṣe, pé ẹ̀yin dúró ṣinṣin nínú Ẹ̀mí kan, ẹ̀yin sì jùmọ̀ n jìjàkadì nítorí ìgbàgbọ́ ìyìn rere, pẹ̀lú ọkàn kan;

28. láìsí ìbẹ̀rẹ̀ àwọn tí ó dojúkọ yin lọ́nà kanna. Èyí sì jẹ́ àmì fún wọn pé a ó pa wọ́n run, a ó sì gbà yín là —èyí tí Ọlọ́run yí ó ṣe.

29. Nítorí a ti fi fún yín nítorí Kírísítì, kì í ṣe láti gbàgbọ́ nínú rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n láti jìyà nítorí rẹ̀ pẹ̀lú.

30. Nípa níní ìjàkadì kan náà tí ẹ̀yin ti rí tí èmi là kọjá, ti ẹ sì gbọ́ nísinsinyìí pé mo sì wà nínú rẹ̀.

Ka pipe ipin Fílípì 1