Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 8:2-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ìránṣẹ́ ibi mímọ́, àti ti àgọ́ tóòtọ́, tí Olúwa pa, kì í ṣe ènìyàn.

3. Nítorí a fi olórí àlùfáà kọ̀ọ̀kan jẹ láti máa mú ẹ̀bùn wá láti máa rúbọ: Nítorí náà ó ṣe pàtàkì fún eléyìí náà láti ní nǹkan tí ó máa fi sílẹ̀.

4. Tí ó bá jẹ́ pé ó wà ní ayé ni, òun kì bá ti jẹ́ àlùfáà, nítorí pé àwọn ọkùnrin tí ó ń fi ẹ̀bùn sílẹ̀ ti wà bí òfin ṣe là á sílẹ̀.

5. Àwọn ẹni tí ń sìn nínú pẹpẹ kan tí ó jẹ́ ẹ̀dá àti òjìji ohun tí ń lọ́run. Ìdí abájọ nìyí tí a fi kìlọ̀ fún Mósè nígbà tí ó kọ́ àgọ́: Nítorí ó wí pé, “Kíyèsí kí o ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí a fihàn ọ lórí òkè.”

6. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí o ti gba iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ó ni ọlá jù, níwọ̀n bí o ti jẹ pé alárinà májẹ̀mú tí o dára jù ní i ṣe, èyí tí a fi ṣe òfin lórí ìlérí tí o sàn jù bẹ́ẹ̀ lọ.

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 8