Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 4:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Nítorí pé àwa tí ó ti gbàgbọ́ wọ inú ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó tí wí,“Bí mo tí búra nínú ìbínú mi,‘Wọn kì yóò wọ inú ìsinmi mi.’ ”Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí parí iṣẹ́ wọ̀nyí láti ìpilẹ̀ ayé.

4. Nítorí ó ti sọ níbìkan ní ti ọjọ́ kéje bayìí pé, “Ọlọ́run sì sinmi ní ọjọ́ keje kúrò nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.”

5. Àti níhìn yìí pẹ̀lú ó wí pé, “Wọn kì yóò wọ inú ìsinmi mi.”

6. Nítorí náà bí ó tí jẹ́ pé, ó ku kí àwọn kan wọ inú rẹ̀, àti àwọn tí a tí wàásù ìyìn rere náà fún ní ìṣáajú kò wọ inú rẹ̀ nítorí àìgbọ́ràn:

7. Àti pé, ó yan ọjọ́ kan, ó wí nínú ìwé Dáfídì pé, “Lònìí,” lẹ́yìn ìgbà pípẹ́ bẹ́ẹ̀; bí a tí wí niṣáájú,“Lònì-ín bí ẹ̀yín bá gbọ́ ohùn rẹ̀,ẹ má ṣe sé ọkàn yín le.”

8. Nítorí, ìbá ṣe pé Jóṣúà tí fún wọn ní ìsinmi, òun kì bá tí sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ ìsinmi mìíràn lẹ̀yìn náà,

9. nítorí náà ìsinmi kan kù fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run.

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 4